< Jesaja 58 >
1 Ropa med full hals utan återhåll, häv upp din röst såsom en basun och förkunna för mitt folk deras överträdelse, för Jakobs hus deras synder.
“Kígbe rẹ̀ sókè, má ṣe fàsẹ́yìn. Gbé ohùn rẹ sókè bí i ti fèrè. Jẹ́ kí ó di mí mọ̀ fún àwọn ènìyàn mi, ọ̀tẹ̀ wọn, àti fún ilé Jakọbu ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
2 Väl söka de mig dag ut och dag in och vilja hava kunskap om mina vägar. Såsom vore de ett folk, som övade rättfärdighet och icke övergåve sin Guds rätt, så fråga de mig om rättfärdighetens rätter och vilja, att Gud skall komma till dem:
Nítorí ọjọ́ dé ọjọ́ ni wọ́n ń wá mi kiri; wọ́n ṣe bí ẹni ní ìtara láti mọ ọ̀nà mi, àfi bí ẹni pé wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè kan tí ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà tí òun kò sì tí ì kọ àṣẹ Ọlọ́run rẹ̀. Wọ́n ń béèrè lọ́wọ́ mi fún ìpinnu nìkan wọ́n sì ṣe bí ẹni ń tara fún Ọlọ́run láti súnmọ́ ọ̀dọ̀ wọn.
3 »Vartill gagnar det, att vi fasta, när du icke ser det, vartill, att vi späka oss, när du icke märker det?» Men se, på edra fastedagar sköten I edra sysslor, och alla edra arbetare driven I blott på.
Wọ́n wí pé, ‘Èéṣe tí àwa fi ń gbààwẹ̀, tí ìwọ kò sì tí ì rí? Èéṣe tí àwa fi rẹra wa sílẹ̀, tí ìwọ kò sì tí ì ṣe àkíyèsí?’ “Síbẹ̀síbẹ̀ ní ọjọ́ àwẹ̀ yín, ẹ̀yin ń ṣe bí ó ti wù yín ẹ sì ń pọ́n àwọn òṣìṣẹ́ yín gbogbo lójú.
4 Och se, I hållen eder fasta med kiv och split, med hugg och slag av gudlösa nävar. I hållen icke mer fasta på sådant sätt, att I kunnen göra eder röst hörd i höjden.
Àwẹ̀ yín sì parí nínú ìjà àti asọ̀, àti lílu ọmọnìkejì ẹni pa pẹ̀lú ìkùùkuu. Ẹ̀yin kò le è gbààwẹ̀ bí ẹ ti ń ṣe lónìí kí ẹ sì retí kí a gbọ́ ohùn un yín ní ibi gíga.
5 Skulle detta vara en fasta, sådan som jag vill hava? Skulle detta vara en rätt späkningsdag? Att man hänger med huvudet såsom ett sävstrå och sätter sig i säck och aska, vill du kalla sådant att hålla fasta, att fira en dag till HERRENS behag?
Ǹjẹ́ èyí ha ni irú àwẹ̀ tí mo yàn bí, ọjọ́ kan ṣoṣo fún ènìyàn láti rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀? Ó ha jẹ pe kí ènìyàn tẹ orí rẹ̀ ba bí i koríko lásán ni bí àti sísùn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú? Ṣé ohun tí ẹ̀ ń pè ní àwẹ̀ nìyí, ọjọ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa?
6 Nej, detta är den fasta, som jag vill hava: att I lossen orättfärdiga bojor och lösen okets band, att I given de förtryckta fria och krossen sönder alla ok,
“Ǹjẹ́ irú àwẹ̀ tí mo ti yàn kọ́ ni èyí: láti já gbogbo ẹ̀wọ̀n àìṣòdodo àti láti tú gbogbo okùn àjàgà, láti tú gbogbo àwọn ti à ń ni lára sílẹ̀ àti láti fọ́ gbogbo àjàgà?
7 ja, att du bryter ditt bröd åt den hungrige och skaffar de fattiga och husvilla härbärge att du kläder den nakne, var du ser honom, och ej drager dig undan för den som är ditt kött och blod.
Kì í ha á ṣe láti pín oúnjẹ yín fún àwọn tí ebi ń pa àti láti pèsè ibùgbé fún àwọn òtòṣì tí ń rìn káàkiri. Nígbà tí ẹ bá rí ẹni tí ó wà níhòhò, láti daṣọ bò ó, àti láti má ṣe lé àwọn ìbátan yín sẹ́yìn?
8 Då skall ljus bryta fram för dig såsom en morgonrodnad, och dina sår skola läkas med hast, och din rätt skall då gå framför dig och HERRENS härlighet följa dina spår.
Nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ rẹ yóò tàn jáde bí òwúrọ̀ àti ìmúláradá rẹ yóò farahàn kíákíá; nígbà náà ni òdodo rẹ yóò sì lọ níwájú rẹ, ògo Olúwa yóò sì jẹ́ ààbò lẹ́yìn rẹ.
9 Då skall HERREN svara, när du åkallar honom; när du ropar, skall han säga: »Se, här är jag.» Om hos dig icke får finnas någon som pålägger ok och pekar finger och talar, vad fördärvligt är,
Nígbà yìí ni ẹ̀yin yóò pè, tí Olúwa yóò sì dáhùn; ẹ̀yin yóò kígbe fún ìrànlọ́wọ́, òun yóò sì wí pé, Èmi nìyí. “Bí ìwọ bá mú àjàgà aninilára, nínà ìka àlébù àti sísọ ọ̀rọ̀ asán kúrò láàrín rẹ,
10 om du delar med dig av din nödtorft åt den hungrige och mättar den som är i betryck, då skall ljus gå upp för dig i mörkret, och din natt skall bliva lik middagens sken.
àti bí ẹ̀yin bá ná ara yín bí owó nítorí àwọn tí ebi ń pa tí ẹ sì tẹ́ ìfẹ́ àwọn tí à ń ni lára lọ́rùn, nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ yín yóò ràn nínú òkùnkùn, àti òru yín yóò dàbí ọ̀sán gangan.
11 Och HERREN skall leda dig beständigt; han skall mätta dig mitt i ödemarken och giva styrka åt benen i din kropp. Och du skall vara lik en vattenrik trädgård och likna ett källsprång, vars vatten aldrig tryter.
Olúwa yóò máa tọ́ ọ yín nígbà gbogbo; òun yóò tẹ́ gbogbo àìní yín lọ́rùn ní ilẹ̀ tí oòrùn ń tan ìmọ́lẹ̀ yóò sì fún egungun rẹ lókun. Ìwọ yóò sì dàbí ọgbà tí a bomirin dáradára, àti bí orísun tí omi rẹ̀ kì í gbẹ.
12 Och dina avkomlingar skola bygga upp de gamla ruinerna, du skall åter upprätta grundvalar ifrån forna släkten; och du skall kallas »han som murar igen revor», »han som återställer stigar, så att man kan bo i landet.»
Àwọn ènìyàn rẹ yóò tún ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì gbé ìpìlẹ̀ àtijọ́-tijọ́ ró a ó sì pè ọ́ ní alátúnṣe ògiri tí ó ti wó àti olùmúbọ̀sípò àwọn òpópónà tí ènìyàn gbé inú rẹ̀.
13 Om du är varsam med din fot på sabbaten, så att du icke på min heliga dag utför dina sysslor; om du kallar sabbaten din lust och HERRENS helgdag en äredag, ja, om du ärar den, så att du icke går dina egna vägar eller sköter dina sysslor eller talar tomma ord,
“Bí ìwọ bá pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́, àti ṣíṣe bí ó ti wù ọ́ ni ọjọ́ mímọ́ mi, bí ìwọ bá pe ọjọ́ ìsinmi ní ohun dídùn àti ọjọ́ mímọ́ Olúwa ní ohun ọ̀wọ̀ àti bí ìwọ bá bu ọlá fún un láti máa bá ọ̀nà tìrẹ lọ àti láti má ṣe bí ó ti wù ọ́ tàbí kí o máa sọ̀rọ̀ aláìníláárí,
14 då skall du finna din lust i HERREN, och jag skall föra dig fram över landets höjder och giva dig till näring din fader Jakobs arvedel. Ja, så har HERRENS mun talat.
nígbà náà ni ìwọ yóò ní ayọ̀ nínú Olúwa rẹ, èmi yóò sì jẹ́ kí ìwọ kí ó máa gun ibi gíga ilẹ̀ ayé, àti láti máa jàdídùn ìní ti Jakọbu baba rẹ.” Ẹnu Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.