< 1 Mosebok 46 >
1 Och Israel bröt upp med allt vad honom tillhörde. Och när han kom till Beer-Seba, offrade han slaktoffer åt sin fader Isaks Gud.
Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
2 Och Gud talade till Israel i en syn om natten; han sade: »Jakob! Jakob!» Han svarade: »Här är jag.»
Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
3 Då sade han: »Jag är Gud, din faders Gud; frukta icke för att draga ned till Egypten, ty där skall jag göra dig till ett stort folk.
Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
4 Jag skall själv draga ned med dig till Egypten, jag skall ock föra dig åter upp därifrån; och Josefs hand skall tillsluta dina ögon.»
Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
5 Och Jakob bröt upp från Beer-Seba; och Israels söner satte sin fader Jakob och sina späda barn och sina hustrur på vagnarna som Farao hade sänt för att hämta honom.
Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
6 Och de togo sin boskap och de ägodelar som de hade förvärvat i Kanaans land och kommo så till Egypten, Jakob och alla hans avkomlingar med honom.
Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
7 Sina söner och sonsöner, sina döttrar och sondöttrar, alla sina avkomlingar, förde han med sig till Egypten.
Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
8 Dessa äro namnen på Israels barn som kommo till Egypten: Jakob och hans söner. Jakobs förstfödde var Ruben,
Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
9 och Rubens söner voro Hanok, Pallu, Hesron och Karmi.
Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
10 Simeons söner voro Jemuel, Jamin, Ohad, Jakin, Sohar och Saul, den kananeiska kvinnans son.
Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
11 Levis söner voro Gerson, Kehat och Merari.
Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
12 Judas söner voro Er, Onan, Sela, Peres och Sera -- men Er och Onan dogo i Kanaans land -- och Peres' söner voro Hesron och Hamul.
Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
13 Isaskars söner voro Tola, Puva, Job och Simron.
Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
14 Sebulons söner voro Sered, Elon och Jaleel.
Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
15 Dessa voro Leas söner, de som hon födde åt Jakob i Paddan-Aram; tillika födde hon åt honom dottern Dina. Söner och döttrar utgjorde tillsammans trettiotre personer.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
16 Gads söner voro Sifjon och Haggi, Suni och Esbon, Eri och Arodi och Areli.
Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
17 Asers söner voro Jimna, Jisva, Jisvi och Beria; och deras syster var Sera; men Berias söner voro Heber och Malkiel.
Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
18 Dessa voro söner till Silpa, som Laban hade givit åt sin dotter Lea, och dessa födde hon åt Jakob, sexton personer.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
19 Rakels, Jakobs hustrus, söner voro Josef och Benjamin.
Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
20 Och de söner som föddes åt Josef i Egyptens land voro Manasse och Efraim; de föddes åt honom av Asenat, dotter till Poti-Fera, prästen i On.
Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
21 Och Benjamins söner voro Bela, Beker och Asbel, Gera och Naaman, Ehi och Ros, Muppim och Huppim och Ard.
Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
22 Dessa voro Rakels söner, de som föddes åt Jakob, tillsammans fjorton personer.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
23 Dans söner voro Husim.
Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
24 Naftalis söner voro Jaseel, Guni, Jeser och Sillem.
Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
25 Dessa voro söner till Bilha, som Laban hade givit åt sin dotter Rakel, och dessa födde hon åt Jakob, tillsammans sju personer.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
26 De som kommo med Jakob till Egypten, de som hade utgått från hans länd, utgjorde alla tillsammans sextiosex personer, förutom Jakobs sonhustrur.
Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
27 Och Josefs söner, vilka föddes åt honom i Egypten, voro två. De personer av Jakobs hus, som kommo till Egypten, utgjorde tillsammans sjuttio.
Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
28 Och han sände Juda framför sig till Josef, för att denne skulle visa honom vägen till Gosen. Så kommo de till landet Gosen.
Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
29 Och Josef lät spänna för sin vagn och for upp till Gosen för att möta sin fader Israel. Och när han kom fram till honom, föll han honom om halsen och grät länge vid hans hals.
Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
30 Och Israel sade till Josef: »Nu vill jag gärna dö, sedan jag har sett ditt ansikte och sett att du ännu lever.»
Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
31 Därefter sade Josef till sina bröder och sin faders folk: »Jag vill fara upp och berätta för Farao och säga till honom: 'Mina bröder och min faders folk, som hittills hava bott i Kanaans land, hava kommit till mig.
Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
32 Och dessa män äro fårherdar, ty de hava idkat boskapsskötsel; och sina får och fäkreatur och allt vad de äga hava de fört med sig.'
Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
33 När sedan Farao kallar eder till sig och frågar: 'Vad är edert yrke?',
Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
34 skolen I svara: 'Vi, dina tjänare, hava idkat boskapsskötsel från vår ungdom ända till nu, vi såväl som våra fäder.' Så skolen I få bo i landet Gosen; ty alla fårherdar äro en styggelse för egyptierna.»
ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”