< 1 Mosebok 3 >

1 Men ormen var listigare än alla andra markens djur som HERREN Gud hade gjort; och han sade till kvinnan: »Skulle då Gud hava sagt: 'I skolen icke äta av något träd i lustgården'?»
Ejò sá à ṣe alárékérekè ju àwọn ẹranko igbó yòókù tí Olúwa Ọlọ́run dá lọ. Ó sọ fún obìnrin náà pé, “Ǹjẹ́ òtítọ́ ha ni Ọlọ́run wí pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ èso èyíkéyìí lára àwọn igi tí ó wà nínú ọgbà’?”
2 Kvinnan svarade ormen: »Vi få äta av frukten på de andra träden i lustgården,
Obìnrin náà dá ejò lóhùn pé, “Àwa lè jẹ lára àwọn èso igi tí ó wà nínú ọgbà,
3 men om frukten på det träd som står mitt i lustgården har Gud sagt: 'I skolen icke äta därav, ej heller komma därvid, på det att I icke mån dö.'»
ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ lára èso igi tí ó wà láàrín ọgbà, ẹ kò sì gbọdọ̀ fi ọwọ́ kàn án, bí ẹ̀yin bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin yóò kùú.’”
4 Då sade ormen till kvinnan: »Ingalunda skolen I dö;
Ejò wí fún obìnrin náà pé, “Ẹ̀yin kì yóò kú ikúkíkú kan.”
5 men Gud vet, att när I äten därav, skola edra ögon öppnas, så att I bliven såsom Gud och förstån vad gott och ont är.»
“Nítorí Ọlọ́run mọ̀ wí pé, bí ẹ̀yin bá jẹ nínú rẹ̀, ojú yín yóò là, ẹ̀yin yóò sì dàbí Ọlọ́run, ẹ̀yin yóò sì mọ rere yàtọ̀ sí búburú.”
6 Och kvinnan såg att trädet var gott att äta av, och att det var en lust för ögonen, och att det var ett ljuvligt träd, eftersom man därav fick förstånd, och hon tog av dess frukt och åt; och hon gav jämväl åt sin man, som var med henne, och han åt.
Nígbà tí obìnrin náà rí i wí pé èso igi náà dára fún oúnjẹ àti pé, ó sì dùn ún wò, àti pé ó ń mú ni ní ọgbọ́n, ó mú díẹ̀ níbẹ̀, ó sì jẹ ẹ́. Ó sì mú díẹ̀ fún ọkọ rẹ̀, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, òun náà sì jẹ ẹ́.
7 Då öppnades bådas ögon, och de blevo varse att de voro nakna; och de fäste ihop fikonlöv och bundo omkring sig.
Nígbà náà ni ojú àwọn méjèèjì sì là, wọ́n sì mọ̀ pé àwọn wà ní ìhòhò; wọ́n sì rán ewé ọ̀pọ̀tọ́ pọ̀, wọ́n sì fi bo ara wọn.
8 Och de hörde HERREN Gud vandra i lustgården, när dagen begynte svalkas; då gömde sig mannen med sin hustru för HERREN Guds ansikte bland träden i lustgården.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ gbọ́ ìró Olúwa Ọlọ́run bí ó ti ń rìn nínú ọgbà, nígbà tí ojú ọjọ́ tura, wọ́n sì fi ara pamọ́ kúrò níwájú Olúwa Ọlọ́run sí àárín àwọn igi inú ọgbà.
9 Men HERREN Gud kallade på mannen och sade till honom: »Var är du?»
Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run ké pe ọkùnrin náà pé, “Níbo ni ìwọ wà?”
10 Han svarade: »Jag hörde dig i lustgården; då blev jag förskräckt, eftersom jag är naken; därför gömde jag mig.»
Ó dáhùn pé, “Mo gbúròó rẹ̀ nínú ọgbà, ẹ̀rù sì bà mí, nítorí pé, mo wà ní ìhòhò, mo sì fi ara pamọ́.”
11 Då sade han: »Vem har låtit dig förstå att du är naken? Har du icke ätit av det träd som jag förbjöd dig att äta av?»
Ọlọ́run wí pé, “Ta ni ó wí fún ọ pé ìhòhò ni ìwọ wà? Ṣé ìwọ ti jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀ ni?”
12 Mannen svarade: »Kvinnan som du har givit mig till att vara med mig, hon gav mig av trädet, så att jag åt.»
Ọkùnrin náà wí pé, “Obìnrin tí ìwọ fi fún mi, ni ó fún mi nínú èso igi náà, mo sì jẹ ẹ́.”
13 Då sade HERREN Gud till kvinnan: »Vad är det du har gjort!» Kvinnan svarade: »Ormen bedrog mig, så att jag åt.»
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe yìí?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Ejò ni ó tàn mí jẹ, mo sì jẹ ẹ́.”
14 Då sade HERREN Gud till ormen: »Eftersom du har gjort detta, vare du förbannad bland alla djur, boskapsdjur och vilda djur. På din buk skall du gå, och stoft skall du äta i alla dina livsdagar.
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí fún ejò náà pé, “Nítorí tí ìwọ ti ṣe èyí, “Ègún ni fún ọ ju gbogbo ohun ọ̀sìn àti gbogbo ẹranko igbó tókù lọ! Àyà rẹ ni ìwọ yóò fi máa wọ́, ìwọ yóò sì máa jẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
15 Och jag skall sätta fiendskap mellan dig och kvinnan, och mellan din säd och hennes säd. Denna skall söndertrampa ditt huvud, och du skall stinga den i hälen.»
Èmi yóò sì fi ọ̀tá sí àárín ìwọ àti obìnrin náà, àti sí àárín irú-ọmọ rẹ àti irú-ọmọ obìnrin náà; òun yóò fọ́ orí rẹ, ìwọ yóò sì bù ú jẹ ní gìgísẹ̀.”
16 Och till kvinnan sade han: »Jag skall låta dig utstå mycken vedermöda, när du bliver havande; med smärta skall du föda dina barn. Men till din man skall din åtrå vara, och han skall råda över dig.»
Ọlọ́run wí fún obìnrin náà pé, “Èmi yóò fi kún ìrora rẹ ní àkókò ìbímọ; ni ìrora ni ìwọ yóò máa bí ọmọ. Ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ ni ìfẹ́ rẹ yóò máa fà sí, òun ni yóò sì máa ṣe àkóso rẹ.”
17 Och till Adam sade han: »Eftersom du lyssnade till din hustrus ord och åt av det träd om vilket jag hade bjudit dig och sagt: 'Du skall icke äta därav', därför vare marken förbannad för din skull. Med vedermöda skall du nära dig av den i alla dina livsdagar;
Ọlọ́run sì wí fún Adamu pé, “Nítorí pé ìwọ fetí sí aya rẹ, ìwọ sì jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀,’ “Ègún ni fún ilẹ̀ nítorí rẹ; nínú ọ̀pọ̀ làálàá ni ìwọ yóò jẹ nínú rẹ̀, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
18 törne och tistel skall den bära åt dig, men markens örter skola vara din föda.
Ilẹ̀ yóò sì hu ẹ̀gún àti èṣùṣú fún ọ, ewéko igbó ni ìwọ yóò sì máa jẹ.
19 I ditt anletes svett skall du äta ditt bröd, till dess du vänder åter till jorden; ty av den är du tagen. Ty du är stoft, och till stoft skall du åter varda.»
Nínú òógùn ojú rẹ ni ìwọ yóò máa jẹun títí tí ìwọ yóò fi padà sí ilẹ̀, nítorí inú ilẹ̀ ni a ti mú ọ jáde wá; erùpẹ̀ ilẹ̀ sá à ni ìwọ, ìwọ yóò sì padà di erùpẹ̀.”
20 Och mannen gav sin hustru namnet Eva, ty hon blev en moder åt allt levande.
Adamu sì sọ aya rẹ̀ ní Efa nítorí òun ni yóò di ìyá gbogbo alààyè.
21 Och HERREN Gud gjorde åt Adam och hans hustru kläder av skinn och satte på dem.
Olúwa Ọlọ́run, sì dá ẹ̀wù awọ fún Adamu àti aya rẹ̀, ó sì fi wọ̀ wọ́n.
22 Och HERREN Gud sade: »Se, mannen har blivit såsom en av oss, så att han förstår vad gott och ont är. Må han nu icke räcka ut sin hand och taga jämväl av livets träd och äta, och så leva evinnerligen.»
Olúwa Ọlọ́run sì wí pé, “Ọkùnrin náà ti dàbí ọ̀kan lára wa, ó mọ rere àti búburú. A kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó na ọwọ́ rẹ̀ kí ó mú lára èso igi ìyè kí ó sì jẹ, kí ó sì wà láààyè títí láéláé.”
23 Och HERREN Gud förvisade honom ur Edens lustgård, för att han skulle bruka jorden, varav han var tagen.
Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run lé e kúrò nínú ọgbà Edeni láti lọ máa ro ilẹ̀ nínú èyí tí a ti mú un jáde wá.
24 Och han drev ut mannen, och satte öster om Edens lustgård keruberna jämte det ljungande svärdets lågor, för att bevaka vägen till livets träd. Namnet härledes från ett hebreiskt ord som betyder leva.
Lẹ́yìn tí ó ti lé ènìyàn jáde tán, ó fi àwọn kérúbù àti idà iná tí ó ń kọ mọ̀nàmọ́ná síwájú àti sẹ́yìn láti ṣọ́ ọ̀nà tí ó lọ sí ibi igi ìyè, ní ìhà ìlà-oòrùn ọgbà Edeni.

< 1 Mosebok 3 >