< 2 Mosebok 3 >

1 Och Mose vaktade fåren åt sin svärfader Jetro, prästen i Midjan. Och han drev en gång fåren bortom öknen och kom så till Guds berg Horeb.
Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
2 Där uppenbarade sig HERRENS ängel för honom i en eldslåga som slog upp ur en buske. Han såg att busken brann av elden, och att busken dock icke blev förtärd.
Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
3 Då tänkte Mose: »Jag vill gå ditbort och betrakta den underbara synen och se varför busken icke brinner upp.»
Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
4 När då HERREN såg att han gick åstad för att se, ropade Gud till honom ur busken och sade: »Mose! Mose!» Han svarade: »Här är jag.»
Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
5 Då sade han: »Träd icke hit; drag dina skor av dina fötter, ty platsen där du står är helig mark.»
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
6 Och han sade ytterligare: »Jag är din faders Gud, Abrahams Gud, Isaks Gud och Jakobs Gud.» Då skylde Mose sitt ansikte, ty han fruktade för att se på Gud.
Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
7 Och HERREN sade: »Jag har nogsamt sett mitt folks betryck i Egypten, och jag har hört huru de ropa över sina plågare; jag vet vad de måste lida.
Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
8 Därför har jag stigit ned för att rädda dem ur egyptiernas våld och föra dem från det landet upp till ett gott och rymligt land, ett land som flyter av mjölk och honung, det land där kananéer, hetiter, amoréer, perisséer, hivéer och jebuséer bo.
Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
9 Fördenskull, eftersom Israels barns rop har kommit till mig, och jag därjämte har sett huru egyptierna förtrycka dem,
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
10 därför må du nu gå åstad, jag vill sända dig till Farao; och du skall föra mitt folk, Israels barn, ut ur Egypten»
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
11 Men Mose sade till Gud: »Vem är jag, att jag skulle gå till Farao, och att jag skulle föra Israels barn ut ur Egypten?»
Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
12 Han svarade: »Jag vill vara med dig. Och detta skall för dig vara tecknet på att det är jag som har sänt dig: när du har fört folket ut ur Egypten, skolen I hålla gudstjänst på detta berg.»
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
13 Då sade Mose till Gud: »När jag nu kommer till Israels barn och säger till dem: 'Edra fäders Gud har sänt mig till eder', och de fråga mig; 'Vad är hans namn?', vad skall jag då svara dem?»
Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
14 Gud sade till Mose: »Jag är den jag är.» Och han sade vidare: »Så skall du säga till Israels barn: 'Jag är' har sänt mig till eder.
Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
15 Och Gud sade ytterligare till Mose: »Så skall du säga till Israels barn: HERREN, edra fäders Gud, Abrahams Gud, Isaks Gud och Jakobs Gud, har sänt mig till eder. Detta skall vara mitt namn evinnerligen, och så skall man nämna mig från släkte till släkte.
Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
16 Gå nu åstad och församla de äldste i Israel, och säg till dem: HERREN, edra fäders Gud, Abrahams, Isaks och Jakobs Gud, har uppenbarat sig för mig, och han har sagt: 'Jag har sett till eder och har sett det som vederfares eder Egypten;
“Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
17 därför är nu mitt ord: jag vill föra eder bort ifrån betrycket i Egypten upp till kananéernas, hetiternas, amoréernas, perisséernas, hivéernas och jebuséernas land, ett land som flyter av mjölk och honung.'
Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
18 Och de skola lyssna till dina ord; och du skall tillika med de äldste i Israel gå till konungen i Egypten, och I skolen säga till honom: HERREN, hebréernas Gud, har visat sig för oss, så låt oss nu gå tre dagsresor in i öknen och offra åt HERREN, vår Gud.'
“Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
19 Dock vet jag att konungen i Egypten icke skall tillstädja eder att gå, icke ens när han får känna min starka hand.
Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
20 Men jag skall räcka ut min hand och slå Egypten med alla slags under, som jag vill göra där; sedan skall han släppa eder.
Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
21 Och jag vill låta detta folk finna nåd för egyptiernas ögon, så att I, när I dragen bort, icke skolen draga bort med tomma händer;
“Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
22 utan var kvinna skall av sin grannkvinna och av den främmande kvinna som bor i hennes hus begära klenoder av silver och guld, så ock kläder. Dessa skolen I sätta på edra söner och döttrar. Så skolen I taga byte från egyptierna.» D. ä. »Han som kallar sig 'Jag är' har sänt mig.» Det här åsyftade hebreiska uttrycket för HERREN, egentligen Jahvé, hos oss vanligen uttalat Jehová, kan översättas med 'Han är'.
Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”

< 2 Mosebok 3 >