< 5 Mosebok 9 >
1 Hör, Israel! Du går nu över Jordan, för att komma ditin och underlägga dig folk, större och mäktigare än du, städer, stora och befästa upp mot himmelen,
Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
2 anakiternas stora och resliga folkstam, som du själv känner, och om vilken du har hört att man säger: »Vem kan stå emot Anaks barn!»
Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
3 Så skall du nu veta att HERREN, din Gud, är den som går framför dig, såsom en förtärande eld; han skall förgöra dem, och han skall förgöra dem, och han skall ödmjuka dem för dig, och du skall fördriva dem och utrota dem med hast, såsom HERREN har lovat dig.
Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
4 Då nu HERREN, din Gud, driver dem undan för dig, må du icke säga vid dig själv: »För min rättfärdighets skull har HERREN låtit mig komma in i detta land och taga det i besittning.» Ty dessa hedningars ogudaktighet är det som gör att HERREN fördriver dem för dig.
Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
5 Icke din rättfärdighet och din rättsinnighet är det som gör att du får komma in i deras land och taga det i besittning, utan dessa hedningars ogudaktighet är det som gör att HERREN, din Gud, fördriver dem för dig. Så vill ock HERREN uppfylla vad han med ed har lovat dina fäder, Abraham, Isak och Jakob.
Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
6 Därför må du nu veta att det icke är din rättfärdighet som gör att HERREN, din Gud, vill giva dig detta goda land till besittning; ty du är ett hårdnackat folk.
Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
7 Kom ihåg, förgät icke, huru du i öknen förtörnade HERREN, din Gud. Allt ifrån den dag då du drog ut ur Egyptens land, ända till dess I nu haven kommit hit, haven I varit gensträviga mot HERREN.
Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
8 Vid Horeb förtörnaden I HERREN, och HERREN vredgades på eder, så att han ville förgöra eder.
Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
9 När jag hade stigit upp på berget för att taga emot stentavlorna, det förbunds tavlor, som HERREN hade slutit med eder, stannade jag på berget i fyrtio dagar och fyrtio nätter, utan att äta och utan att dricka.
Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
10 Och HERREN gav mig de två stentavlorna, på vilka Gud hade skrivit med sitt finger; vad där stod var alldeles lika med de ord HERREN hade talat med eder på berget ur elden, den dag då I voren församlade där.
Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
11 Och när de fyrtio dagarna och de fyrtio nätterna voro förlidna, gav HERREN mig de två stentavlorna, förbundets tavlor.
Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
12 Och HERREN sade till mig: »Stå upp och gå med hast ned härifrån, ty ditt folk, som du har fört ut ur Egypten, har tagit sig till, vad fördärvligt är. De hava redan vikit av ifrån den väg som jag bjöd dem gå; de hava gjort sig ett gjutet beläte.»
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
13 Och HERREN talade till mig och sade: »jag har sett att detta folk är ett hårdnackat folk.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
14 Lämna mig i fred, ty jag vill förgöra dem och utplåna deras namn, så att det icke mer finnes under himmelen; dig vill jag sedan göra till ett folk som är mäktigare och större än detta.»
Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
15 Då vände jag mig om och steg ned från berget, som brann i eld; och jag hade i mina båda händer förbundets två tavlor.
Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
16 Och jag fick då se att I haven syndat mot HERREN, eder Gud: I haden gjort eder en gjuten kalv; så haden I redan vikit av ifrån den väg som HERREN hade bjudit eder gå.
Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
17 Då fattade jag i de båda tavlorna och kastade dem ifrån mig med båda händerna och slog sönder dem inför edra ögon.
Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
18 Och jag föll ned inför HERRENS ansikte och låg så, likasom förra gången i fyrtio dagar och fyrtio nätter, utan att äta och utan att dricka, för all den synds skulle som I haden begått genom att göra vad ont var i HERRENS ögon, till att förtörna honom.
Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
19 Ty jag fruktade för den vrede och förbittring mot eder, av vilken HERREN hade blivit så uppfylld att han ville förgöra eder. Och HERREN hörde mig även denna gång.
Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Också på Aron blev HERREN mycket vred, så att han ville förgöra honom, och jag bad då jämväl för Aron.
Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
21 Sedan tog jag kalven, syndabelätet som I haden gjort, och brände den i eld och krossade sönder den väl, till dess att den blev fint stoft, och det stoftet kastade jag i bäcken som flöt ned från berget.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
22 I Tabeera, i Massa och i Kibrot-Hattaava förtörnaden I ock HERREN.
Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
23 Och när HERREN ville sända eder åstad från Kades-Barnea och sade: »Dragen upp och intagen det land som jag har givit eder», då voren I gensträviga mot HERREN, eder Guds, befallning och trodden honom icke och hörden icke hans röst.
Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
24 Ja, gensträviga haven I varit mot HERREN allt ifrån den dag då jag lärde känna eder.
Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
25 Så föll jag då ned inför HERRENS ansikte och låg så i de fyrtio dagarna och de fyrtio nätterna; ty HERREN hade sagt att han ville förgöra eder.
Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
26 Och jag bad till HERREN och sade: »Herre, HERRE, fördärva icke ditt folk och din arvedel, som du har förlossat med din stora makt, och som du med stark hand har fört ut ur Egypten.
Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
27 Tänk på dina tjänare Abraham, Isak och Jakob, se icke på detta folks hårdhet, ogudaktighet och synd;
Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
28 på det att man icke må säga i det land varur du har fört oss ut: 'Därför att HERREN, icke förmådde föra dem in i det land som han hade lovat åt dem, och därför att han hatade dem, förde han dem ut och lät dem dö i öknen.'
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
29 De äro ju ditt folk och din arvedel, som du har fört ut med din stora kraft och din uträckta arm.»
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”