< 5 Mosebok 20 >

1 Om du drager ut i krig mot dina fiender, och du då får se hästar och vagnar och ett folk som är större än du. så skall du dock icke frukta för dem, ty HERREN, din Gud, är med dig, han som har fört dig upp ur Egyptens land.
Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
2 När I då stån färdiga att gå i striden, skall prästen träda fram och tala till folket;
Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
3 han skall säga till dem: »Hör, Israel! I stån nu färdiga att gå i strid mot edra fiender. Edra hjärtan vare icke försagda; frukten icke och ängslens icke, och varen icke förskräckta för dem,
yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
4 ty HERREN, eder Gud, går själv med eder; till att strida för eder mot edra fiender och giva eder seger.»
Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
5 Och tillsyningsmännen skola tala till folket och säga: »Om någon finnes här, som har byggt sig ett nytt hus, men ännu icke invigt det, så må han vända tillbaka hem, för att icke. om han faller i striden, en annan må komma att inviga det.
Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
6 Och om någon finnes här, som har planterat en vingård, men ännu icke fått skörda någon frukt därav, så må han vända tillbaka hem, för att icke, om han faller i striden, en annan må komma att hämta första skörden av den.
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
7 Och om någon finnes här, som har trolovat sig med en kvinna, men ännu icke tagit henne till sig, så må han vända tillbaka hem, för att icke om han faller i striden, en annan man må taga henne till sig.»
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
8 Vidare skola tillsyningsmännen tala till folket och säga: »Om någon finnes här, som fruktar och har ett försagt hjärta, så må han vända tillbaka hem, för att icke också hans bröders hjärtan må bliva uppfyllda av räddhåga, såsom hans eget hjärta är.»
Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
9 Och när tillsyningsmännen så hava talat till folket, skola hövitsmän tillsättas övar härens avdelningar, till att gå i spetsen för folket.
Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
10 När du kommer till någon stad för att belägra den, skall du först tillbjuda den fred.
Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
11 Om den då giver dig ett fridsamt svar och öppnar sina portar för dig, så skall allt folket som finnes där bliva arbetspliktigt åt dig och vara dina tjänare.
Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
12 Men om den icke vill hava fred med dig, utan vill föra krig mot dig, så må du belägra den.
Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
13 Och om HERREN, din Gud, då giver den i din hand, skall du slå allt mankön där med svärdsegg.
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
14 Men kvinnorna och barnen och boskapen och allt annat som finnes i staden, allt rov du får där, skall du hava såsom ditt byte; och du må då njuta av det rov som HERREN. din Gud, låter dig taga från dina fiender.
Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
15 Så skall du göra med alla de städer som äro mer avlägsna från dig, och som icke höra till dessa folks städer.
Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
16 Men i de städer som tillhöra dessa folk, och som HERREN, din Gud, vill giva dig till arvedel, skall du icke låta något som anda har bliva vid liv,
Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
17 utan du skall giva dem alla till spillo: hetiterna och amoréerna, kananéerna och perisséerna, hivéerna och jebuséerna, såsom HERREN din Gud, har bjudit dig.
Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
18 Så skall du göra, för att de icke må lära eder att bedriva alla de styggelser som de själva hava bedrivit till sina gudars ära, och så komma eder att synda mot HERREN, eder Gud.
Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
19 Om du måste länge belägra en stad för att erövra och intaga den, så skall du icke förstöra träden däromkring genom att höja din yxa mot dem; du må äta av deras frukt, men du skall icke hugga ned dem; träden på marken äro ju icke människor som skola belägras av dig.
Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
20 Men de träd om vilka du vet att de icke bära ätbar frukt, dem må du förstöra och hugga ned för att av dem bygga bålverk mot den fientliga staden, till dess att den faller
Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.

< 5 Mosebok 20 >