< 2 Kungaboken 6 >
1 Profetlärjungarna sade till Elisa: »Se, rummet där vi sitta inför dig är för trångt för oss.»
Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
2 Låt oss därför gå till Jordan och därifrån hämta var sin timmerstock, så att vi där kunna bygga oss ett annat hus att sitta i.» Han svarade: »Gån åstad.»
Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
3 Men en av dem sade: »Värdes själv gå med dina tjänaren.» Han varade: »Ja, jag skall gå med.»
Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
4 Så gick han med dem. Och när de kommo till Jordan, begynte de hugga ned träd.
Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
5 Men under det att en av dem höll på att fälla en stock, föll yxjärnet i vattnet. Då gav han upp ett rop och sade: »Ack, min herre, yxan var ju lånad.»
Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
6 Gudsmannen frågade: »Var föll den i?» Och han visade honom stället. Då högg han av ett stycke trä och kastade det i där och fick så järnet att flyta upp.
Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
7 Sedan sade han: »Tag nu upp det.» Då räckte mannen ut sin hand och tog det.
Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
8 Och konungen i Aram låg i krig med Israel. Men när han rådförde sig med sina tjänare och sade: »På det och det stället vill jag lägra mig»,
Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
9 då sände gudsmannen bud till Israels konung och lät säga: »Tag dig till vara för att tåga fram vid det stället, ty araméerna ligga där.»
Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
10 Då sände Israels konung till det ställe som gudsmannen hade angivit för honom och varnat honom för; och han tog sig till vara där. Detta skedde icke allenast en gång eller två gånger.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
11 Häröver blev konungen i Aram mycket orolig; och han kallade till sig sina tjänare och sade till dem: »Kunnen I icke säga mig vem av de våra det är som håller med Israels konung?»
Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
12 Då svarade en av hans tjänare: »Icke så, min herre konung; men Elisa, profeten i Israel, kungör för Israels konung vart ord som du talar i din sovkammare.»
Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
13 Han sade: »Gån och sen till, var han finnes, så att jag kan sända åstad och gripa honom.» Och man berättade för honom att han var i Dotan.
Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
14 Då sände han dit hästar och vagnar och en stor här; och de kommo dit om natten och omringade staden.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
15 När nu gudsmannens tjänare bittida om morgonen stod upp och gick ut, fick han se att en här hade lägrat sig runt omkring staden med hästar och vagnar. Då sade tjänaren till honom: »Ack, min herre, huru skola vi nu göra?»
Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
16 Han svarade: »Frukta icke; ty de som äro med oss äro flera än de som äro med dem.»
“Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
17 Och Elisa bad och sade: »HERRE, öppna hans ögon, så att han ser.» Då öppnade HERREN tjänarens ögon, och han fick se att berget var fullt med hästar och vagnar av eld, runt omkring Elisa.
Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
18 När de nu drogo ned mot honom, bad Elisa till HERREN och sade: »Slå detta folk med blindhet.» Då slog han dem med blindhet, såsom Elisa bad.
Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
19 Och Elisa sade till dem: »Detta är icke den rätta vägen eller den rätta staden. Följen mig, så skall jag föra eder till den man som I söken.» Därefter förde han dem till Samaria.
Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
20 Men när de kommo till Samaria, sade Elisa: »HERRE, öppna dessas ögon, så att de se.» Då öppnade HERREN deras ögon, och de fingo se att de voro mitt i Samaria.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
21 När då Israels konung såg dem, sade han till Elisa: »Skall jag hugga ned dem, min fader, skall jag hugga ned dem?»
Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
22 Han svarade: »Du skall icke hugga ned dem. Du plägar ju icke ens hugga ned dem som du har tagit till fånga med svärd och båge. Sätt fram för dem mat och dryck och låt dem äta och dricka, och låt dem sedan gå till sin herre igen»
“Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
23 Då tillredde han åt dem en stor måltid, och när de hade ätit och druckit, lät han dem gå; och de gingo till sin herre igen. Sedan kommo icke vidare några arameiska strövskaror in i Israels land.
Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
24 Därefter hände sig att Ben-Hadad, konungen i Aram, samlade hela sin här och drog upp och belägrade Samaria.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
25 Och medan de belägrade Samaria, uppstod där en så stor hungersnöd, att man betalade åttio siklar silver för ett åsnehuvud och fem siklar silver för en fjärdedels kab duvoträck.
Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
26 Och en gång då Israels konung gick omkring på muren ropade en kvinna till honom och sade: »Hjälp, min herre konung!»
Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
27 Han svarade: »Hjälper icke HERREN dig, varifrån skall då jag kunna skaffa hjälp åt dig? Från logen eller från vinpressen?»
Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
28 Och konungen frågade henne: »Vad fattas dig?» Hon svarade: »Kvinnan där sade till mig: 'Giv hit din son, så att vi få äta honom i dag, så skola vi äta min son i morgon.'
Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
29 Så kokade vi min son och åto upp honom. Nästa dag sade jag till henne: 'Giv nu hit din son, så att vi få äta honom.' Men då gömde hon undan sin son.»
Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
30 När konungen hörde kvinnans ord, rev han sönder sina kläder, där han gick på muren. Då fick folket se att han hade säcktyg inunder, närmast kroppen.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
31 Och han sade: »Gud straffe mig nu och framgent, om Elisas, Safats sons, huvud i dag får sitta kvar på honom.»
Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
32 Så sände han då dit en man före sig, under det att Elisa satt i sitt hus och de äldste sutto där hos honom. Men innan den utskickade hann fram till honom, sade han till de äldste: »Sen I huru denne mördarson sänder hit en man för att taga mitt huvud? Men sen nu till, att I stängen igen dörren, när den utskickade kommer; och spärren så vägen för honom med den. Jag hör nu ock ljudet av hans herres steg efter honom.»
Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
33 Medan han ännu talade med dem, kom den utskickade ned till honom. Och denne sade: »Se, detta är en olycka som kommer från HERREN; huru skall jag då längre kunna hoppas på HERREN?»
Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”