< 2 Kungaboken 21 >
1 Manasse var tolv år gammal, när han blev konung, och han regerade femtiofem år i Jerusalem. Hans moder hette Hefsi-Ba.
Manase jẹ́ ẹni ọdún méjìlá nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Hẹfisiba.
2 Han gjorde vad ont var i HERRENS ögon, efter den styggeliga seden hos de folk som HERREN hade fördrivit för Israels barn.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ó sì tẹ̀lé iṣẹ́ ìríra tí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
3 Han byggde åter upp de offerhöjder som hans fader Hiskia hade förstört, och reste altaren åt Baal och gjorde en Asera, likasom Ahab, Israels konung, hade gjort, och tillbad och tjänade himmelens hela härskara.
Ó sì tún ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah tí ó parun kọ́. Ó sì tún gbé pẹpẹ Baali dìde, ó sì ṣe ère òrìṣà Aṣerah, gẹ́gẹ́ bí Ahabu ọba Israẹli ti ṣe. Ó sì tẹríba sí gbogbo ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.
4 Ja, han byggde altaren i HERRENS hus, det om vilket HERREN hade sagt: »Vid Jerusalem vill jag fästa mitt namn.»
Ó sì kọ́ pẹpẹ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ní Jerusalẹmu ni èmi yóò kọ orúkọ mi sí.”
5 Han byggde altaren åt himmelens hela härskara på de båda förgårdarna till HERRENS hus.
Ní àgbàlá méjèèjì ilé Olúwa, ó sì kọ́ pẹpẹ fún gbogbo àwọn ìrúbọ nínú ilé, ṣe iṣẹ́ àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì béèrè lọ́wọ́ àwọn òkú àti àwọn oṣó. Ó sì ṣe ọ̀pọ̀ búburú ní ojú Olúwa, ó sì mú un bínú.
6 Han lät ock sin son gå genom eld och övade teckentyderi och svartkonst och skaffade sig andebesvärjare och spåmän och gjorde mycket som var ont i HERRENS ögon, så att han förtörnade honom.
Ó fi àwọn ọmọ ara rẹ̀ rú ẹbọ nínú iná, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
7 Och Aserabelätet som han hade låtit göra satte han i det hus om vilket HERREN hade sagt till David och till hans son Salomo: »Vid detta hus och vid Jerusalem som jag har utvalt bland alla Israels stammar, vill jag fästa mitt namn för evig tid
Ó sì gbé ère fínfín òrìṣà Aṣerah tí ó ti ṣe, ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí èmi ti yàn jáde lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò kọ orúkọ mi títí láéláé.
8 Och jag skall icke mer låta Israel vandra flyktig bort ifrån det land som jag har givit åt deras fäder, om de allenast hålla och göra allt vad jag har bjudit dem, och det alldeles efter den lag som min tjänare Mose har givit dem.»
Èmi kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli yẹ̀ kúrò láti ilẹ̀ tí èmi fi fún àwọn baba ńlá wọn tí ó bá jẹ́ wí pé wọn yóò ṣe àkíyèsí láti ṣe gbogbo ohun tí èmi ti paláṣẹ fún wọn kí wọn sì pa gbogbo òfin tí ìránṣẹ́ mi Mose fi fún wọn mọ́.”
9 Men de lyssnade icke härtill, och Manasse förförde dem, så att de gjorde mer ont än de folk som HERREN hade förgjort för Israels barn.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tẹ́tí. Manase tàn wọ́n síwájú, bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n lè ṣe búburú ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa tí parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli lọ.
10 Då talade HERREN genom sina tjänare profeterna och sade:
Olúwa sì wí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì pé,
11 »Eftersom Manasse, Juda konung, har bedrivit dessa styggelser och så gjort mer ont, än allt vad amoréerna som voro före honom hava gjort, så att han med sina eländiga avgudar har kommit också Juda att synda,
“Manase ọba Juda ti ṣe ẹ̀ṣẹ̀ ohun ìríra. Ó ti ṣe ohun búburú jùlọ ju àwọn ará Amori lọ ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ tí ó sì ti ṣáájú Juda sínú ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú àwọn ère rẹ̀.
12 därför säger HERREN, Israels Gud, så: 'Se, jag skall låta en sådan olycka komma över Jerusalem och Juda, att det skall genljuda i båda öronen på var och en som får höra det.
Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, Èmi le è lọ mú irú ibi báyìí wá sórí Jerusalẹmu àti Juda kí gbogbo etí olúkúlùkù tí ó gbọ́ nípa rẹ̀ le è hó.
13 Och mot Jerusalem skall jag bruka det mätsnöre som jag brukade mot Samaria, och det sänklod som jag brukade mot Ahabs hus; och jag skall skölja Jerusalem tomt, såsom man sköljer ett fat och, sedan man har sköljt det, vänder det upp och ned.
Èmi yóò sì nà okùn ìwọ̀n kan tí a lò lórí Jerusalẹmu àti lórí Samaria àti òjé ìdiwọ̀n ti a lò lórí ilé Ahabu. Èmi yóò sì nu Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọkàn tí ń nu àwokòtò nù tí o ń nù un tí o sì ń dorí rẹ̀ kodò.
14 Och jag skall förskjuta kvarlevan av min arvedel och giva dem i deras fienders hand, så att de skola bliva ett rov och ett byte för alla sina fiender --
Èmi yóò sì kọ ìyókù àwọn ìní mi sílẹ̀ èmi yóò sì kó wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́. Wọn yóò sì di ìkógun àti ìjẹ fún gbogbo àwọn ọ̀tá wọn,
15 detta därför att de hava gjort vad ont är i mina ögon och beständigt förtörnat mig, från den dag då deras fader drogo ut ur Egypten ända till denna dag.'»
nítorí pé wọ́n ti ṣe búburú ní ojú mi, wọ́n sì ti mú mi bínú láti ọjọ́ tí baba ńlá wọn ti jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí.”
16 Därtill utgöt ock Manasse oskyldigt blod i så stor myckenhet, att han därmed uppfyllde Jerusalem från den ena ändan till den andra -- detta förutom den särskilda syns genom vilken han kom Juda att synda och göra vad ont var i HERRENS ögon.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, Manase pẹ̀lú ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ púpọ̀ tí ó kún Jerusalẹmu láti ìkangun dé ìkangun ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti mú Juda ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni, kí wọ́n lè ṣe ohun búburú ní ojú Olúwa.
17 Vad nu mer är att säga om Manasse och om allt vad han gjorde så ock om den synd han begick det finnes upptecknat i Juda konungars krönika.
Ní ti iṣẹ́ ìyókù ti ìjọba Manase, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ṣé wọ́n kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
18 Och Manasse gick till vila hos sina fäder och blev begraven i trädgården till sitt hus, i Ussas trädgård. Och hans son Amon blev konung efter honom.
Manase sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ọgbà ààfin rẹ̀, ọgbà Ussa. Amoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
19 Amon var tjugutvå år gammal när han blev konung, och han regerade två år i Jerusalem. Hans moder hette Mesullemet, Harus' dotter, från Jotba.
Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Orúkọ màmá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Meṣulemeti ọmọbìnrin Harusi: ó wá láti Jotba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
20 Han gjorde vad ont var i HERRENS ögon, såsom hans fader Manasse hade gjort.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa àti gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe.
21 Han vandrade i allt på samma väg som hans fader hade vandrat, och tjänade och tillbad de eländiga avgudar som hans fader hade tjänat.
Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà baba rẹ̀: Ó sì ń sin àwọn ère tí baba rẹ̀ ń sìn, ó sì ń tẹrí rẹ̀ ba fún wọn.
22 Han övergav HERREN, sina fäders Gud, och vandrade icke på HERRENS väg.
Ó sì kọ Olúwa Ọlọ́run baba rẹ̀ sílẹ̀ kò sì rìn ní ọ̀nà ti Olúwa.
23 Och Amons tjänare sammansvuro sig mot honom och dödade konungen hemma i hans hus.
Àwọn ìránṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ lórí rẹ̀ wọ́n sì lu ọba pa ní àárín ilé rẹ̀.
24 Men folket i landet dräpte alla som hade sammansvurit sig mot konung Amon. Därefter gjorde folket i landet hans son Josia till konung efter honom.
Nígbà náà àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí ó dìtẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì fi Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ààyè rẹ̀.
25 Vad nu mer är att säga om Amon, om vad han gjorde, det finnes upptecknat i Juda konungars krönika. Och man begrov honom i hans grav i Ussas trädgård. Och hans son Josia blev konung efter honom. Se Mätsnöre i Ordförkl.
Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ti ìjọba Amoni àti ohun tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
Wọ́n sì sin ín sínú isà òkú nínú ọgbà Ussa. Josiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.