< Sefanja 2 >

1 Församler eder, och kommer hit, I obehageliga folk;
Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
2 Förr än domen utgår, så att I om dagen bortryken såsom ett stoft, förr än Herrans grymma vrede öfver eder kommer, förr än Herrans vredes dag öfver eder kommer;
kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà, kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín, kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
3 Söker Herran, alle I elände i landena, I som hans rätter hållen; söker rättfärdighetena, söker ödmjukhetena; på det att I på Herrans vredes dag mågen beskyddade varda.
Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà, ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ. Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú, bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
4 Ty Gaza måste öfvergifven varda, och Askelon förödd; Asdod skall om middagen förjagad varda, och Ekron utrotad varda.
Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀, Aṣkeloni yóò sì dahoro. Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde, a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
5 Ve dem som bo nedre vid hafvet, de krigare. Herrans ord skall komma öfver eder. Du Canaan, de Philisteers land, jag skall förgöra dig, så att der ingen mer bo skall.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun, ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti; ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani, ilẹ̀ àwọn ara Filistini. “Èmi yóò pa yín run, ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
6 Der skola nedre vid hafvet vara alltsammans herdahus, och fårahus.
Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti, ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
7 Och det samma skall varda dem qvarlefdom af Juda hus till del, att de deruppå beta skola. Om aftonen skola de lägra sig uti Askelons husom, då nu Herren deras Gud dem återsökt, och deras fängelse vänd hafver.
Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda, níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran. Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́. Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò, yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
8 Jag hafver hört Moabs hädelse, och Ammons barnas försmädelse, der de med hafva försmädat mitt folk, och berömt sig öfver deras gränsor.
“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni, àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
9 Nu väl, så sant som jag lefver, säger Herren Zebaoth, Israels Gud: Moab skall varda lika som Sodom, och Ammons barn lika som Gomorra; ja, lika som en nässlebuske, och en saltgrufva, och ett evigt öde; de qvarlefde af mitt folk skola beröfva dem, och de öfverblefne af mitt folk skola ärfva dem.
Nítorí náà, bí Èmi tí wà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí, “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu, àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra, ibi tí ó kún fún yèrèpè, àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé. Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn; àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
10 Det skall vederfaras dem för deras högfärd, att de hafva försmädat Herrans Zebaoths folk, och berömt sig öfver dem.
Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn, nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 Förskräckelig skall Herren vara öfver dem; ty han skall förlägga alla gudar på jordene; och alla öar ibland Hedningarna skola tillbedja honom, hvar och en i sitt rum.
Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn; nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run. Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn, olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
12 Ock skolen I Ethiopier genom mitt svärd slagne varda.
“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú, a ó fi idà mi pa yín.”
13 Och han skall sträcka sina hand norrut, och förgöra Assur; han skall göra Nineve öde, torrt, såsom en öken;
Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá, yóò sì pa Asiria run, yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.
14 Så att sig deruti lägra skola allahanda djur ibland Hedningarna; och rördrommar och ufvar skola bo på deras torn, och skola sjunga i vigskården, och korpar på bjelkomen; ty cedrebräden skola afrifne varda.
Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀, àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè. Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀. Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé, ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà, òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
15 Denne är den lustige staden, den så säker bodde, och sade i sitt hjerta: Jag äret, och ingen annan. Huru är han så öde vorden, så att djuren bo derinne; och hvilken som der framom går, han hvisslar till honom, och slår med handene öfver honom?
Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu. Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé, “Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.” Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́, ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó! Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀ yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.

< Sefanja 2 >