< Sakaria 6 >

1 Och jag lyfte åter min ögon upp, och såg; och si, der voro fyra vagnar, som gingo ut emellan tu berg; och bergen voro af koppar.
Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
2 För första vagnen voro röde hästar; för den andra vagnen voro svarte hästar;
Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
3 För den tredje vagnen voro hvite hästar; för den fjerde vagnen voro brokote, starke hästar.
Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
4 Och jag svarade, och sade till Ängelen, som med mig talade: Min Herre, ho äro desse?
Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
5 Ängelen svarade, och sade till mig: Det äro de fyra väder under himmelen, som utgå, att de framträda skola för honom, som råder öfver all land.
Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
6 Der de svarte hästarna före voro, de gingo norråt, och de hvite gingo efter dem; men de brokote gingo söderåt.
Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
7 De starke gingo, och drogo omkring, så att de foro igenom all land; och han sade: Går åstad, och drager igenom landet. Och de drogo igenom landet.
Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
8 Och han kallade mig, och talade med mig, och sade: Si, de som norråt draga, de låta min Anda hvilas i nordlandena.
Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
9 Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
10 Tag af fångomen, nämliga af Heldai och af Tobia, och af Jedaja; och kom du, på den samma dagen, och gack in uti Josia, Zephania sons hus, hvilke af Babel komne äro.
“Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
11 Men tag silfver och guld, och gör ( två ) kronor, och sätt dem uppå Josua, dens öfversta Prestens, hufvud, Jozadaks sons;
Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
12 Och säg till honom: Detta säger Herren Zebaoth: Si, der är en man, som heter Zemah; under honom skall det gro, och han skall bygga Herrans tempel.
Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
13 Ja, Herrans tempel skall han bygga; han skall bära skruden, och skall sitta och råda på sinom stol; skall också vara en Prest på sinom stol, och der skall frid vara emellan dem båda.
Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
14 Och kronorna skola vara Helem, Tobia, Jedaja, och Hen, Zephania sone, till en åminnelse i Herrans tempel.
Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
15 Och de skola komma fjerranefter, som uppå Herrans tempel bygga skola. Så skolen I förnimma, att Herren Zebaoth mig till eder sändt hafver; och det skall ske, så framt I hörande varden Herrans edars Guds röst.
Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”

< Sakaria 6 >