< Sakaria 2 >
1 Och jag hof min ögon upp, och si, en man hade ett mätesnöre i handene.
Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
2 Och jag sade: Hvart går du? Men han sade till mig: Till att mäta Jerusalem, och se huru bredt och långt det vara skall.
Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
3 Och si, Ängelen, som med mig talade, gick ut; och en annar Ängel gick ut emot honom;
Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
4 Och sade till honom: Löp bort, och tala till den unga mannen, och säg: Jerusalem skall besuttet varda utan murar, för mycket folks och fäs skull, som derinne vara skall.
Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
5 Och jag vill, säger Herren, vara en eldsmur deromkring; och skall vara der inne, och bevisa mig härliga derinne.
Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
6 O, o, flyr utu nordlandet, säger Herren; ty jag hafver förstrött eder uti fyra väder under himmelen, säger Herren.
“Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
7 O, Zion, du som bor när dottrene Babel, fly.
“Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
8 Ty så säger Herren Zebaoth: Han hafve sändt mig till Hedningarna, som eder beröfvat hafva; deras magt hafver en ända i den eder rörer, han rörer hans ögnasten.
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
9 Ty si, jag vill upphäfva mina hand öfver dem, att de skola varda dem ett rof, som dem tjent hafva; att I skolen förnimma att Herren Zebaoth mig sändt hafver.
Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
10 Fröjda dig, och var glad, du dotter Zion; ty si, jag kommer, och vill bo när dig, säger Herren.
“Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
11 Och på den tiden skola månge Hedningar gifva sig intill Herran, och skola vara mitt folk; och jag skall bo när dig, att du skall förnimma, att Herren Zebaoth mig till dig sändt hafver.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
12 Och Herren skall ärfva Juda för sin del, uti de helga landena; och skall åter utvälja Jerusalem.
Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
13 Allt kött vare stilla för Herranom; ty han är uppstånden ifrå sitt helga rum.
Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”