< Psaltaren 69 >

1 En Psalm Davids, om roserna, till att föresjunga. Gud, hjelp mig, ty vatten går allt intill mina själ.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Jag sjunker ned i djup dy, der ingen botten uti är; jag är kommen i djup vatten, och floden vill fördränka mig.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Jag hafver ropat mig tröttan, min hals är hes, synen förgås mig; att jag så länge måste bida efter min Gud.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 De som mig utan skuld hata, äro flere än jag håren på hufvudet hafver; de som mig med oskäl förfölja och förderfva, äro mägtige; jag måste betala det jag intet röfvat hade.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Gud, du vetst min galenskap, och mina skulder äro dig intet förskylda.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Låt dem icke på mig till skam komma, som dig förbida, Herre, Herre Zebaoth; låt dem icke till blygd komma, som dig söka, Israels Gud.
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Ty för dina skuld lider jag försmädelse; mitt ansigte är fullt med blygd.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 Jag är minom brödrom främmande vorden, och okänd mins moders barnom.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Ty dins hus nitälskan uppfräter mig, och deras försmädelser, som dig häda, falla uppå mig.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Och jag gret, och fastade bitterliga; och man begabbade mig dertill.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Jag drog en säck uppå; men de gjorde der lek af.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 De som i porten sitta, tassla om mig, och i dryckenskap qväder man om mig.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Men jag beder, Herre, till dig, i behagelig tid; Gud, efter dina stora godhet, hör mig med dine trofasta hjelp.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Upptag mig utu träcken, att jag icke nedersjunker; att jag må frälst varda ifrå mina hatare, och utu de djupa vatten;
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Att vattufloden icke fördränker mig, och djupet icke uppsluker mig, och gapet på gropene icke igentäppes öfver mig.
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Hör mig, Herre, ty din godhet är tröstelig. Vänd dig till mig efter dina stora barmhertighet;
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Och bortgöm icke ditt ansigte för dinom tjenare; ty mig är ångest. Hör mig snarliga.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Nalka dig till mina själ, och förlossa henne; förlossa mig för mina fiendars skull.
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Du vetst min försmädelse, skam och blygd; alle mine fiender äro för dig.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Försmädelse bråkar mig hjertat sönder, och kränker mig; jag vänter, att någor ville varkunna sig, men der är ingen; och efter hugsvalare, men jag finner ingen.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Och de gåfvo mig galla äta, och ättiko dricka uti minom stora törst.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Deras bord varde för dem en snara, till vedergällning, och till ena fällo.
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Deras ögon varde mörk, så att de intet se; och deras länder låt städse ostadiga vara.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Utgjut dina ogunst uppå dem, och din grymma vrede gripe dem.
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Deras boning varde öde, och ingen vare som uti deras hyddom bor.
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Ty de förfölja den du slagit hafver, och berömma att du slår dina illa.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Låt dem falla uti den ena synden efter den andra, att de icke komma till dina rättfärdighet.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Utskrapa dem utu de lefvandes bok; att de med de rättfärdiga icke uppskrefne varda.
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Men jag är elände, och hafver ondt; Gud, din hjelp beskydde mig.
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 Jag vill lofva Guds Namn med en viso, och vill högeliga ära honom med tacksägelse.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 Det skall bättre täckas Herranom, än en stut, den horn och klöfvar hafver.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 De elände se det, och glädja sig; och de som Gud söka, dem skall hjertat lefva.
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 Ty Herren hörer de fattiga, och föraktar icke sina fångna.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Honom lofve himmelen, jorden och hafvet, och allt det deruti röres.
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Ty Gud skall hjelpa Zion, och bygga Juda städer; att man der bo skall, och besitta dem.
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 Och hans tjenares säd skall ärfva dem; och de som hans Namn älska, skola blifva derinne.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Psaltaren 69 >