< Psaltaren 109 >

1 En Psalm Davids, till att föresjunga. Gud, mitt lof, tig icke;
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
2 Ty de hafva upplåtit sin ogudaktiga och falska mun emot mig, och tala emot mig med falska tungor.
nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
3 Och de tala hätskeliga emot mig allestäds, och strida emot mig utan sak.
Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
4 Derföre, att jag älskar dem, äro de emot mig; men jag beder.
Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
5 De bevisa mig ondt för godt, och hat för min kärlek.
Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
6 Sätt ogudaktiga öfver honom, och Satan stånde på hans högra hand.
Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 Den som sig af honom lära låter, hans lefverne vare ogudaktigt, och hans bön vare synd.
Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
8 Varde hans dagar få, och hans ämbete tage en annar.
Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
9 Varde hans barn faderlös, och hans hustru enka.
Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
10 Hans barn gånge husvill och tigge, och söke, såsom de der förderfvade äro.
Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
11 De ockrare utsuge allt det han hafver, och de främmande bortröfve hans gods.
Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
12 Och ingen bevise honom godt, och ingen förbarme sig öfver hans faderlösa.
Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
13 Hans efterkommande varde utrotade; deras namn varde i androm led utplånad.
Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
14 På hans fäders missgerning varde tänkt för Herranom, och hans moders synd varde intet utplånad.
Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
15 Herren låte dem aldrig komma utu sin ögnasyn, och deras åminnelse varde utrotad på jordene;
Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
16 Derföre att han så platt ingen barmhertighet hade; utan förföljde den elända och fattiga, och den bedröfvada, till att dräpa honom.
Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
17 Och han ville hafva förbannelse, den skall ock komma honom; han ville icke välsignelse, så skall hon ock vara långt ifrå honom.
Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
18 Och han drog förbannelse uppå sig, såsom sina skjorto; och hon är ingången i hans inelfver, såsom vatten, och såsom olja uti hans ben.
Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
19 Hon varde honom såsom en klädnad, den han uppå sig hafver, och såsom ett bälte, der han allestädes omgjordar sig med.
Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
20 Alltså ske dem af Herranom, som mig emot äro, och tala ondt emot mina själ.
Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
21 Men du, Herre, Herre, var du med mig för ditt Namns skull; ty din nåd är min tröst, fräls mig.
Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
22 Ty jag är fattig och elände; mitt hjerta är bedröfvadt i mig.
Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
23 Jag går bort såsom en skugge, den fördrifven varder, och varder förjagad såsom gräshoppor.
Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
24 Min knä äro svage af fasto, och mitt kött är magert, och hafver ingen fetma.
Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
25 Och jag måste vara deras begabberi; när de se mig, rista de sitt hufvud.
Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
26 Gör mig bistånd, Herre, min Gud; hjelp mig efter dina nåd;
Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
27 Att de måga förnimma, att det är din hand; att du, Herre, detta gör.
Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
28 Förbanna de, så välsigna du; sätta de sig emot mig, så varde de till skam; men din tjenare glädje sig.
Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
29 Mine motståndare varde med försmädelse beklädde, och varde med sine skam öfvertäckte, såsom med en kjortel.
Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
30 Jag vill mycket tacka Herranom med min mun, och lofva honom ibland många.
Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
31 Ty han står dem fattiga på högra handene, att han skall hjelpa honom ifrå dem som hans lif fördöma.
Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.

< Psaltaren 109 >