< Psaltaren 106 >
1 Halleluja. Tacker Herranom, ty han är mild, och hans godhet varar i evighet.
Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 Ho kan uttala Herrans dråpeliga gerningar? och prisa all hans lofliga verk?
Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
3 Salige äro de som budet hålla, och göra alltid rätt.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
4 Herre, tänk på mig efter den nåd, som du dino folke lofvat hafver; bevisa oss dina hjelp;
Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
5 Att vi måge se dina utkorades välfärd, och glädja oss att dino folke väl går, och berömma oss med dinom arfvedel.
kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
6 Vi hafve syndat med våra fäder; vi hafve misshandlat, och hafve ogudaktige varit.
Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
7 Våre fäder uti Egypten ville icke förstå din under; de tänkte icke på dina stora godhet, och voro ohörige vid hafvet, nämliga röda hafvet.
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
8 Men han halp dem för sitt Namns skull, så att han sina magt beviste.
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
9 Och han näpste röda hafvet, och det vardt torrt; och förde dem genom djupen, såsom genom ena öken;
O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
10 Och halp dem ifrå deras hand, som dem hatade, och förlossade dem ifrå fiendans hand.
O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
11 Och vattnet fördränkte deras fiendar, så att icke en qvar blef.
Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Då trodde de uppå hans ord, och söngo hans lof.
Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
13 Men de förgåto snarliga hans gerningar, och bidde intet efter hans råd.
Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
14 Och de fingo lusta i öknene, och försökte Gud uti ödemarkene.
Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
15 Men han gaf dem deras bön, och sände dem nog, tilldess dem vämjade dervid.
Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
16 Och de satte sig upp emot Mose i lägrena; emot Aaron, Herrans heliga.
Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Jorden öppnade sig, och uppsvalg Dathan, och öfvertäckte Abirams rota.
Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
18 Och eld vardt ibland deras rota upptänd; lågen uppbrände de ogudaktiga.
Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 De gjorde en kalf i Horeb, och tillbådo det gjutna belätet;
Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 Och förvandlade sina äro uti ens oxas liknelse, den gräs äter.
Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 De förgåto Gud sin Frälsare, som så stor ting uti Egypten gjort hade;
Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 Vidunder i Hams land, och förskräckeliga gerningar i röda hafvet.
iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
23 Och han sade, att han ville förgöra dem, om Mose hans utkorade den plågan icke förtagit hade, och afvändt hans grymhet, att han icke platt skulle förderfva dem.
Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
24 Och de föraktade det lustiga landet; de trodde icke hans ordom;
Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 Och knorrade i deras hyddom; de lydde intet Herrans röst.
Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 Och han hof upp sina hand emot dem, att han skulle nederslå dem i öknene;
Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 Och kasta deras säd ibland Hedningarna, och förströ dem i landen.
láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
28 Och de gåfvo sig till BaalPeor, och åto af de döda afgudars offer;
Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
29 Och förtörnade honom med sin verk; då kom ock en plåga ibland dem.
wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 Då trädde Pinehas fram, och förlikte sakena, och plågan vände åter.
Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
31 Och det vardt honom räknadt till rättfärdighet, ifrå slägte till slägte, i evig tid.
A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 Och de förtörnade honom vid trätovattnet; och de plågade Mose illa.
Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 Ty de bedröfvade honom hans hjerta, så att någor ord undföllo honom.
Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
34 De förgjorde ock icke de folk, som dock Herren dem budit hade;
Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
35 Utan de blandade sig ibland Hedningarna, och lärde deras verk;
Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
36 Och tjente deras afgudom; de kommo dem på förargelse.
Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 Och de offrade sina söner, och sina döttrar djeflom;
Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 Och utgöto oskyldigt blod, sina söners och döttrars blod, som de offrade Canaans afgudom; så att landet med blodskulder besmittadt vardt;
Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
39 Och orenade sig med sinom gerningom, och hor bedrefvo med sin verk.
Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
40 Då förgrymmade sig Herrans vrede öfver sitt folk, och han fick en styggelse till sitt arf;
Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 Och gaf dem uti Hedningars händer; så att öfver dem rådde de som dem hätske voro.
Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 Och deras fiender plågade dem, och de vordo kufvade under deras händer.
Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 Han förlossade dem ofta; men de förtörnade honom med sin verk, och vordo få för deras missgerningars skull.
Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Och han såg till deras nöd, då han deras klagan hörde;
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
45 Och tänkte på sitt förbund, som han med dem gjort hade; och det ångrade honom efter hans stora godhet;
ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 Och lät dem komma till barmhertighet, för allom dem som dem fångat hade.
Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
47 Hjelp oss, Herre vår Gud, och för oss tillhopa ut ifrå Hedningarna; att vi måge tacka ditt helga Namn, och begå ditt lof.
Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
48 Lofvad vare Herren, Israels Gud, ifrån evighet i evighet; och allt folk säga: Amen. Halleluja.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!