< Klagovisorna 3 >

1 Jag är en elände man, den hans grymhets ris se måste.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Han hafver ledt mig, och låtit mig gå i mörkrena, och icke i ljusena.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Han hafver vändt sina hand emot mig, och handlar fast annorlunda med mig alltid.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Han hafver gjort mitt kött och mina hud gammal, och sönderslagit min ben.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Han hafver byggt emot mig, och bevefvat mig uti galla och mödo.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Han hafver lagt mig uti mörkret, lika som de döda i verldene.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Han hafver innemurat mig, så att jag icke utkomma kan, och satt mig uti hårda fjettrar.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Och om jag än ropade och både, så stoppar han öronen till för mina bön.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Han hafver igenmurat min väg med huggen sten, och mina stigar igentäppt.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Han hafver vaktat efter mig lika som en björn, lika som ett lejon i lönlig rum.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Han hafver låtit mig fela om vägen; han hafver rifvit mig i stycken sönder, och tillintetgjort.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Han hafver spänt sin båga, och satt mig; såsom ett mål för pilenom.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Han hafver utaf kogret låtit skjuta mig i mina njurar.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Jag är vorden till spott allo mino folke, och deras dagliga visa.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Han hafver måttat mig med bitterhet, och gifvit mig malört dricka.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Han hafver slagit mina tänder sönder i små stycke, och vältrat mig uti asko.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Min själ är fördrifven ifrå fridenom; goda, dagar måste jag förgäta.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Jag sade: Mitt hopp är ute, att jag någon tid mer skall vara när Herranom.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Kom dock ihåg, huru jag är elände och öfvergifven, och malört och galla druckit hafver.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Du varder ju deruppå tänkandes; ty min själ säger mig det.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Det lägger jag på hjertat, derföre hoppas mig ännu.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Herrans mildhet är det, att ännu icke är ute med oss; hans barmhertighet hafver än nu icke ända;
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Utan hon är hvar morgon ny, och din trohet är stor.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Herren är min del, säger min själ; derför vill jag hoppas uppå honom.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Ty Herren är god dem som hoppas uppå honom, och den själ som frågar efter honom.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Det är en kostelig ting, att man är tålig, och hoppas uppå Herrans hjelp.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Det är en kostelig ting, att man drager oket i ungdomen;
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Att en, som öfvergifven är, hafver tålamod, när honom något uppåkommer;
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Och sätter sin mun uti stoft, och vänter efter hoppet;
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Och låtter slå sig vid kindbenet, och lägger mycken försmädelse uppå sig.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Ty Herren drifver icke ifrå sig evinnerliga;
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Utan han bedröfvar väl; men han förbarmar sig igen, efter sin stora mildhet.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Ty han plågar och bedröfvar icke menniskona af hjertat;
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Lika som han ville platt undertrycka låta de elända på jordene;
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Och låta deras sak för Gudi orätta vara;
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 Och dem falskeliga döma låta, lika som Herren såge det intet.
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Ho tör då säga, att sådant sker utan Herrans befallning;
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Och att hvarken ondt eller godt kommer igenom hans befallning?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Hvi knorra då menniskorna alltså, medan de lefva? Hvar och en knorre emot sina synder.
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Och låt oss ransaka och söka vårt väsende, och omvända oss till Herran.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Låt oss upplyfta vår hjerta, samt med händerna, till Gud i himmelen.
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Vi, vi hafve syndat, och olydige varit; derföre hafver du med rätta intet skonat;
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Utan du hafver förmörkrat oss med vrede, och förföljt och dräpit utan barmhertighet.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Du hafver betäckt dig med en sky, att ingen bön derigenom komma kunde.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Du hafver gjort oss till träck och slemhet ibland folken.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Alle våre fiender gapa med munnen emot oss.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Vi varde förtryckte och plågade med förskräckelse och ångest.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Min ögon rinna med vattubäcker, öfver mins folks dotters jämmer.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Min ögon flyta, och kunna icke aflåta; ty der är ingen återvända;
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 Tilldess Herren af himmelen skådar härned, och ser dertill.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Mitt öga fräter mig lifvet bort, för alla mins stads döttrars skull.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Mine fiender hafva besnärt mig, lika som en fågel, utan sak.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 De hafva förgjort mitt lif uti ene kulo, och kastat uppå mig stenar.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 De hafva ock begjutit mitt hufvud med vatten; då sade jag: Nu är det platt ute med mig.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Men jag åkallade ditt Namn, Herre, nedan utu kulone;
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Och du hörde mina röst: Bortgöm icke din öron för mitt suckande och ropande.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Nalka dig till mig, när jag åkallar dig och säg; Frukta dig intet.
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Uträtta, du Herre, mins själs sak, och förlossa mitt lif.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Herre, se dock till, huru orätt mig sker, och hjelp mig till min rätt.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Du ser alla deras hämnd, och alla deras tankar emot mig.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Herre, du hörer deras försmädelse, och alla deras tankar öfver mig;
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Mina motståndares läppar, och deras rådslag emot mig dagliga.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Se dock, ehvad de sig lägga eller uppstå, så qväda de visor om mig.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Vedergäll dem, Herre, såsom de förtjent hafva.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Låt dem deras hjerta förskräckas och känna dina banno.
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Förfölj dem med grymhet, och förgör dem under Herrans himmel.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< Klagovisorna 3 >