< Job 31 >
1 Jag hafver gjort ett förbund med min ögon, att jag intet skall sköta efter någon jungfru.
“Mo ti bá ojú mi dá májẹ̀mú, èmi yó ha ṣe tẹjúmọ́ wúńdíá?
2 Men hvad gifver mig Gud till löna ofvan efter, och hvad arfvedel den Allsmägtige af höjdene?
Nítorí pé kí ni ìpín Ọlọ́run láti ọ̀run wá? Tàbí kí ni ogún Olódùmarè láti òkè ọ̀run wá.
3 Skulle icke heldre den orättfärdige hafva den vedermödona, och en ogerningsman sådana jämmer lida?
Kò ṣe pé àwọn ènìyàn búburú ni ìparun wà fún, àti àjàkálẹ̀-ààrùn fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀?
4 Ser han icke mina vägar, och räknar alla mina gånger?
Òun kò ha ri ipa ọ̀nà mi, òun kò ha sì ka gbogbo ìṣísẹ̀ mi?
5 Hafver jag vandrat i fåfängelighet, eller min fot skyndat sig till bedrägeri?
“Bí ó bá ṣe pé èmi bá fi àìṣòótọ́ rìn, tàbí tí ẹsẹ̀ mi sì yára sí ẹ̀tàn,
6 Man väge mig på en rätt våg, så skall Gud förnimma min fromhet.
(jẹ́ kí Ọlọ́run wọ́n mí nínú ìwọ̀n òdodo, kí Ọlọ́run le mọ ìdúró ṣinṣin mi.)
7 Hafver min gång vikit utaf vägen, och mitt hjerta efterföljt min ögon, och något lådat vid mina händer,
Bí ẹsẹ̀ mí bá yà kúrò lójú ọ̀nà, tí àyà mí sì tẹ̀lé ipa ojú mi, tàbí bí àbàwọ́n kan bá sì lẹ̀ mọ́ mi ní ọwọ́,
8 Så låt mig så, och en annar äte det; och min ätt varde utrotad.
ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmíràn kí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú-ọmọ mi tu.
9 Hafver mitt hjerta låtit sig draga till qvinno, och hafver vaktat vid mins nästas dörr,
“Bí àyà mi bá di fífà sí ipasẹ̀ obìnrin kan, tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu-ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,
10 Så varde min hustru af enom androm skämd, och andre besofve henne;
kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fún ẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.
11 Ty det är en last och en missgerning för domarena.
Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àní, ẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀.
12 Ty det vore en eld, som förtärer intill förderf, och all min tilldrägt utrotade.
Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibi ìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbò ohun ìbísí mi gbogbo tu.
13 Hafver jag föraktat, mins tjenares eller mine tjenarinnos rätt, då de med mig trätte?
“Tí mo bá sì ṣe àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrin mi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;
14 Hvad ville jag göra, när Gud reser sig upp? Och hvad ville jag svara, när han hemsöker?
kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́run bá dìde? Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?
15 Hafver ock icke han gjort honom, den mig i moderlifvet gjorde; och hafver ju så väl tillredt honom i lifvena?
Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a? Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?
16 Hafver jag dem torftigom förnekat hvad de begärde, och låtit enkones ögon försmäkta?
“Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́ inú tálákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó rẹ̀wẹ̀sì,
17 Hafver jag ätit min beta allena, att den faderlöse icke också hafver ätit deraf?
tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mi jẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;
18 Ty ifrå minom ungdom hafver jag hållit mig såsom en fader, och allt ifrå mitt moderlif hafver jag gerna hugsvalat.
nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá ni a ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹni pé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:
19 Hafver jag någon sett förgås, derföre att han icke hade kläder; och låtit den fattiga gå oskyldan?
bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ, tàbí tálákà kan láìní ìbora;
20 Hafva icke hans sidor välsignat mig, då han af min lambs skinn värmad vardt?
bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi, tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípasẹ̀ irun àgùntàn mi;
21 Hafver jag låtit komma mina hand vid den faderlösa, ändock jag såg mig i portenom magt hafva,
bí mo bá sì gbé ọwọ́ mi sókè sí aláìní baba, nítorí pé mo rí ìrànlọ́wọ́ mi ní ẹnu ibodè,
22 Så falle mina skuldror ifrå mina axlar, och min arm gånge sönder ifrå läggenom.
ǹjẹ́, ní apá mi kí o wọ́n kúrò ní ihò èjìká rẹ̀, kí apá mi kí ó sì ṣẹ́ láti egungun rẹ̀ wá.
23 Ty jag fruktade Gud såsom en olycko öfver mig, och kunde hans tunga icke bära.
Nítorí pé ìparun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ẹ̀rù ńlá fún mi, àti nítorí ọláńlá rẹ̀ èmi kò le è dúró.
24 Hafver jag satt guld till min tröst, och sagt till guldklimpen: Du äst mitt hopp?
“Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi, tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi,’
25 Hafver jag gladt mig, att jag myckna ägodelar hade, och min hand allahanda förvärfvat hade?
bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀, àti nítorí ọwọ́ mi dara lọ́pọ̀lọ́pọ̀,
26 Hafver jag sett på ljuset, då det klarliga sken, och på månan, då han i fyllo gick?
bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tí ń ràn, tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,
27 Hafver mitt hjerta hemliga låtit sig tälja i det sinnet, att min mun skulle kyssa mina hand?
bí a bá tàn ọkàn mi jẹ láti fi ẹnu mi kò ọwọ́ mi,
28 Hvilket ock en missgerning är för domarena; förty dermed hade jag nekat Gud i höjdene.
èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn onídàájọ́ ní láti bẹ̀wò, nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.
29 Hafver jag gladt mig, när minom fiende gick illa, och upphäfvit mig, att olycka råkade uppå honom?
“Bí ó bá ṣe pé mo yọ̀ sì ìparun ẹni tí ó kórìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéraga sókè, nígbà tí ibi bá a.
30 Ty jag lät min mun icke synda, så att han önskade hans själ ena banno.
Bẹ́ẹ̀ èmi kò sì jẹ ki ẹnu mi ki ó ṣẹ̀ nípa fífẹ́ ègún sí ọkàn rẹ̀.
31 Hafva icke de män i mine hyddo måst säga: Ack! att vi icke måtte af hans kött mättade varda.
Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bá lè wí pé, ‘Ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?’
32 Ute måste den främmande icke blifva; utan dem vägfarande lät jag mina dörr upp.
Àlejò kò wọ̀ ni ìgboro rí; èmí ṣí ìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.
33 Hafver jag såsom en menniska skylt mina skalkhet, att jag skulle hemliga fördölja min missgerning?
Bí mo bá bò ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ bí Adamu ni pápá, ẹ̀bi mi pamọ́ ni àyà mi.
34 Hafver jag grufvat mig för stora hopen; eller hafver frändernas föraktelse mig förskräckt? Jag blef stilla, och gick icke ut genom dörrena.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni mo ha bẹ̀rù bí? Tàbí ẹ̀gàn àwọn ìdílé ní ń bà mí ní ẹ̀rù? Tí mo fi pa ẹnu mọ́, tí èmí kò sì fi sọ̀rọ̀ jáde?
35 Ho gifver mig en förhörare, att den Allsmägtige må höra mitt begär? Att någor måtte skrifva en bok om mine sak;
(“Ìbá ṣe pé ẹnìkan le gbọ́ ti èmí! Kíyèsi i, àmì mi, kí Olódùmarè kí ó dá mi lóhùn, kí èmí kí ó sì rí ìwé náà tí olùfisùn mi ti kọ.
36 Så ville jag taga henne uppå mine axlar, och ombinda mig henne såsom en krono.
Nítòótọ́ èmí ìbá gbé le èjìká mi, èmi ìbá sì dé bí adé mọ́ orí mi.
37 Jag ville förkunna talet på mina gånger, och såsom en Förste ville jag det frambära.
Èmi ìbá sì sọ iye ìṣísẹ̀ mi fún un, bí ọmọ-aládé ni èmi ìbá súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.)
38 Om min jord ropar emot mig, och dess fårar alle tillika gråta;
“Bí ilẹ̀ mi bá sì ké rara lòdì sí mi tí a sì fi omijé kún gbogbo poro rẹ̀.
39 Hafver jag dess frukt obetalad ätit, och gjort åkermännernas lefverne tungt;
Bí mo bá jẹ èso oko mi láìsan owó tàbí tí mo sì mú ọkàn olúwa rẹ̀ fò lọ,
40 Så växe mig tistel för hvete, och törne för bjugg. En ända hafva Jobs ord.
kí ẹ̀gún òṣùṣú kí ó hù dípò alikama, àti èpò búburú dípò ọkà barle.” Ọ̀rọ̀ Jobu parí.