< Job 3 >

1 Derefter upplät Job sin mun, och förbannade sin dag;
Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
2 Utbrast, och sade:
Jobu sọ, ó sì wí pé,
3 Den dagen vare förtappad, på hvilkom jag född är; och den natten, då man sade: En man är aflad.
“Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé, àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
4 Den samme dagen vare mörk, och Gud fråge intet efter honom ofvanefter; ingen klarhet skine öfver honom.
Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn, kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá; bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
5 Mörkret behålle honom, och töcken blifve öfver honom med tjockt moln; och dimba om dagen göre honom gräselig.
Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn; kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e; kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
6 Den samma nattena begripe mörker; och glädje sig icke ibland årsens dagar, och komme icke i månadetalet.
Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri, kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà: kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
7 Si, vare den natten ensam, och ingen glädje komme deruti.
Kí òru náà kí ó yàgàn; kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
8 De der dagen förbanna, de förbanne henne; och de som redo äro till att uppväcka Leviathan.
Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún, tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
9 Hennes stjernor varde mörka; förvänte ljus, och det komme intet; och se intet morgonrodnans ögnabryn;
Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn; kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
10 Att hon icke igenlyckte mins lifs dörr, och icke bortgömde olyckona för min ögon.
nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi, láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.
11 Hvi blef jag icke straxt död i moderlifvet? Hvi vardt jag icke förgjord, då jag utu moderlifvet kommen var?
“Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá, tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
12 Hvi hafva de tagit mig upp i skötet? Hvi hafver jag ditt spenar?
Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi, tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
13 Så låge jag nu, och vore stilla; sofve och hade ro;
Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́; èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
14 Med Konungar och rådherrar på jordene, som bygga det öde är;
pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
15 Eller med Förstar, som guld hafva, och sin hus full med silfver;
Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn.
16 Eller som den der otida född är fördold, och vore icke till; såsom de unga barn, som aldrig hafva sett ljuset.
Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí: bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
17 Der måste ju de ogudaktige låta af sitt öfvervåld; der hvilas dock de som mycket omak haft hafva.
Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu, níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
18 Der hafva fångar frid med androm, och höra icke trugarens röst.
Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀, wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
19 Der äro både små och store; tjenaren och den som ifrå sin herra fri är.
Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀, ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.
20 Hvi är ljus gifvet dem arma, och lif de bedröfvade hjerta;
“Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì, àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
21 (De der vänta efter döden, och han kommer icke; och uppgrofvo honom väl utu fördold rum;
tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá, tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
22 De der fröjda sig mycket, och äro glade, att de kunna få grafvena; )
Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi, tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
23 Och dem månne, hvilkens väg fördold är, och för honom af Gudi skyld varder?
Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún, tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
24 Förty min suckan är min dagliga spis; mine tårar äro min dryck.
Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi; ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
25 Ty det jag fruktade, det är kommet öfver mig; och det jag räddes, hafver råkat på mig.
Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí, àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
26 Var jag icke lyckosam? Var jag icke stilla? Hade jag icke goda ro? Och sådana oro kommer.
Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”

< Job 3 >