< Jeremia 42 >
1 Då trädde fram alle höfvitsmännerna, Johanan, Kareahs son, Jesanja, Hosaja son, samt med allo folkena, både små och stora;
Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
2 Och sade till Propheten Jeremia: Käre, låt våra bön något gälla för dig, och bed för oss Herran din Gud, om alla dessa igenlefda; ty, dess värr! vi äre få igenblefne af mångom, såsom du sjelfver oss ser med din ögon;
Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
3 Att Herren din Gud ville kungöra oss, hvart vi draga, och hvad vi göra skole.
Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
4 Och Propheten Jeremia sade till dem: Nu väl, jag vill höra eder; och si, jag vill bedja Herran edar Gud, såsom I sagt hafven; och allt det Herren eder svarar, det vill jag kungöra eder, och vill intet dölja undan för eder.
Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
5 Och de sade till Jeremia: Herren vare ett visst och sant vittne emellan oss, om vi icke göre allt det Herren din Gud genom dig oss befallandes varder;
Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
6 Vare sig godt eller ondt, så vilje vi lyda Herrans vår Guds röst, den vi sände dig till; på det oss må väl gå, då vi Herrans vår Guds röst lyde.
Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
7 Efter tio dagar skedde Herrans ord till Jeremia.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
8 Då kallade han Johanan, Kareahs son, och alla höfvitsmännerna, som när honom voro, och allt folket, både små och stora;
O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
9 Och sade till dem: Detta säger Herren, Israels Gud, till hvilken I mig sändt hafven, att jag skulle bära edor bön fram för honom:
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
10 Om I blifven i dessa lande, så vill jag uppbygga och icke omkullslå eder; Jag skall plantera och icke upprycka eder; ty det onda, som jag eder gjort hafver, det ångrar mig allaredo.
Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
11 I skolen väl säkre vara för Konungenom i Babel, den I rädens före, säger Herren; I skolen intet frukta honom; ty jag vill vara när eder, att jag skall hjelpa och frälsa eder ifrå hans hand.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
12 Jag skall bevisa eder barmhertighet, och förbarma mig öfver eder, och föra eder uti edart land igen.
Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
13 Men om I sägen: Vi vilje icke blifva i desso landena; på det I ju icke skolen lyda Herrans edars Guds röst;
“Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
14 Utan sägen: Nej, vi vilje draga in uti Egypti land, på det vi intet örlig se måge, eller höra basuners ljud, och ingen hunger för bröds brists skull lida, der vilje vi blifva;
Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
15 Nu, så hörer Herrans ord, I qvarblefne af Juda; detta säger Herren Zebaoth, Israels Gud: Om I ställen edor ansigte till att draga in uti Egypten, så att I viljen der blifva;
nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
16 Så skall svärdet, der I frukten eder före, drabba på eder uti Egypti land; och hungren, den I rädens före, skall allestädes följa eder uti Egypten, och skolen der dö.
Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
17 Ty vare sig ho de kunna, som sitt ansigte dit ställa, att de vilja draga in uti Egypten, der till att blifva, de skola dö genom svärd, hunger och pestilentie; och ingen skall qvar blifva, eller undslippa det onda, som jag skall öfver dem komma låta.
Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
18 Ty så säger Herren Zebaoth, Israels Gud: Likasom min vrede och grymhet är gången öfver Jerusalems inbyggare, så skall hon ock gå öfver eder, om I dragen in uti Egypten; på det I skolen varda till bannor, till under, till svärjande, och till skam, och aldrig mer få se detta rummet.
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
19 Herrans ord gäller eder till, I qvarblefne af Juda, att I icke dragen in uti Egypten; derföre veter, att jag i dag betygar eder;
“Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
20 Eljest sen I edra själar illa före; ty I sänden mig till Herran edar Gud, och saden: Bed Herran vår Gud för oss; och allt det Herren vår Gud sägandes varder, det kungör oss, så vilje vi göra derefter.
pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
21 Det hafver jag nu i dag låtit eder få veta; men I hafven intet velat höra Herrans edars Guds röst, eller allt det han mig till eder befallt hafver.
Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
22 Så skolen I nu veta, att I genom svärd, hunger och pestilentie, dö måsten, uti det rum, dit I akten att draga, att I der bo skolen.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”