< Jeremia 21 >
1 Detta är det ord, som af Herranom skedde till Jeremia, då Konung Zedekia sände till honom Pashur, Malchia son, och Zephanja, Maaseja Prestens son, och lät säga honom:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 Fråga dock Herran för oss; ty NebucadNezar, Konungen i Babel, örligar emot oss; att Herren dock ville göra med oss efter all sin under, på det han må draga ifrån oss.
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 Jeremia sade till dem: Detta säger till Zedekia:
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Så säger Herren Israels Gud: Si, jag skall vända de vapen tillbaka, som I uti edra händer hafven, der I med striden emot Konungen i Babel, och emot de Chaldeer, som eder omkring murarna belagt hafva; och skall församla dem i en hop midt i stadenom.
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 Och jag skall strida emot eder med uträckto hand, med starkom arm, med stor vrede, grymhet och obarmhertighet;
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 Och skall slå inbyggarena i denna stadenom, både folk och fä, så att de skola dö i en stor pestilentie.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 Och derefter, säger Herren, skall jag gifva Zedekia, Juda Konung, samt med hans tjenare, och folkena, som i denna stadenom af pestilentie, svärd och hunger qvarlefde äro, uti NebucadNezars händer, Konungens i Babel, och uti deras fiendars händer, och uti deras händer som efter deras lif stå, att han så skall slå dem med svärdsegg, att der ingen skonan, eller nåde, eller barmhertighet med skall vara.
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 Och säg desso folkena: Så säger Herren: Si, jag sätter eder före vägen till lifvet, och vägen till döden.
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Hvilken som blifver i denna stadenom, han måste dö igenom svärd, hunger och pestilentie; men den som gifver sig ut till de Chaldeer, som eder belägga, han skall blifva lefvandes, och skall behålla sitt lif, likasom ett byte.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 Ty jag hafver ställt mitt ansigte öfver denna staden till olycko, och till intet godt, säger Herren; han skall Konungenom i Babel öfvergifven varda, att han skall uppbränna honom med eld.
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 Och hörer Herrans ord, I af Juda Konungs huse.
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Du Davids hus, detta säger Herren: Håller domen om morgonen, och hjelper den beröfvada utu våldsverkarens hand, på det min grymhet icke skall utfara lika som en eld, och brinna så, att det ingen utsläcka kan, för edart onda väsendes skull.
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Si, säger Herren: Jag säger dig, du som bor i dalenom, på bergen och på jemna markene, och säger: Ho vill öfverfalla oss, eller komma in uti vårt fäste?
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Jag vill hemsöka eder, säger Herren, efter edra gerningars frukt; jag skall upptända en eld uti edar skog, han skall förtära allt det deromkring är.
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”