< Jeremia 11 >
1 Detta är det ord som till Jeremia skedde af Herranom, som sade:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
2 Hörer detta förbunds ord, att I mågen säga dem till Juda och Jerusalems inbyggare;
“Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
3 Och säg till dem: Så säger Herren Israels Gud: Förbannad vare den som icke lyder detta förbunds ord,
Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
4 Som jag edra fäder böd på den dag jag dem utur Egypti land förde, utur jernugnen, och sade: Hörer mina röst, och görer som jag eder budit hafver; så skolen I vara mitt folk, och jag vill vara edar Gud;
Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
5 På det jag må hålla den ed, som jag edra fäder svorit hafver till att gifva dem ett land, der mjölk och hannog uti flyter, såsom det i denna dag för ögon är. Jag svarade, och sade: Ja, Herre, det ske alltså.
Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
6 Och Herren sade till mig: Predika alla dessa orden uti Juda städer, och uppå gatorna i Jerusalem, och säg: Hörer detta förbunds ord, och görer derefter.
Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
7 Ty jag hafver betygat edra fäder, ifrå den dagen jag dem utur Egypti land förde, intill denna dag, och betygade städse, och sade: Hörer mina röst.
Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
8 Men de hörde intet, och böjde ej heller sin öron härtill, utan hvar och en gick efter sins onda hjertas tycko; derföre vill jag ock öfver dem gå låta, all detta förbunds ord, det jag dem böd att de göra skulle, och de dock derefter icke gjort hafva.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
9 Herren sade till mig: Jag vet väl, huru de i Juda och Jerusalem gadda sig tillhopa.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
10 De vända sig till sina förfäders synder, hvilke min ord ej heller höra ville, utan följde också andra gudar efter, och tjente dem; alltså hafver Israel hus och Juda hus nu ( allstädes ) brutit mitt förbund, det jag med deras fäder gjort hafver.
Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
11 Derföre, si, säger Herren: Jag vill låta en olycko gå öfver dem, den de icke undkomma skola; och när de ropa till mig, så vill jag intet höra dem.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
12 Så låt då Juda städer och Jerusalems inbyggare gå bort, och ropa till de gudar, hvilkom de rökt hafva; men de skola intet hjelpa dem i deras nöd.
Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
13 Ty så många städer, så många gudar hafver du, Juda, och så många gator som i Jerusalem äro, så mång blygdealtare hafven I uppsatt, till att röka för Baal.
Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
14 Så bed nu du intet för detta folk, och haf ingen åkallan eller bön för dem; ty jag vill intet höra dem, när de ropa till mig i sine nöd.
“Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
15 Hvad hafva mine vänner till att skaffa i mitt hus? De bedrifva alla falskhet, och mena det heliga köttet skall taga det bort af dem; och när de illa göra, så äro de glade deröfver.
“Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
16 Herren kallade dig ett grönt, skönt, fruktsamt oljoträ; men nu hafver han med ett stort mordskri, upptändt en eld deromkring, så att dess qvistar måste förderfvade varda.
Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
17 Ty Herren Zebaoth, som dig planterat hafver, hafver lofvat dig ondt, för Israels hus, och Juda hus ondskos skull, den de bedrifva, så att de förtörna mig, i det de röka för Baal.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
18 Herren hafver mig det uppenbarat, så att jag det vet; och viste mig hvad de hafva för händer;
Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
19 Nämliga att de vilja slagta mig, likasom ett armt får; ty jag visste icke, att de emot mig rådslagit hade, och sagt: Låt oss förderfva trät med sine frukt, och utrota honom utu de lefvandes land, att på hans namn skall aldrig mer tänkt varda.
Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
20 Men du, Herre Zebaoth, du rättvise domare, du som bepröfvar njurar och hjerta, låt mig se dina hämnd öfver dem; ty jag hafver befallt dig mina sak.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
21 Derföre säger Herren alltså emot dem i Anathoth, hvilke efter ditt lif stå, och säga: Spå oss intet i Herrans Namn, om du annars icke dö vill af våra händer.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
22 Derföre säger Herren Zebaoth alltså: Si, jag vill hemsöka dem; deras unge män skola med svärd dräpne varda, och deras söner och döttrar af hunger dö;
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
23 Så att intet af dem skall qvart blifva; ty jag skall låta en olycko gå öfver dem i Anathoth, på det året då de skola hemsökte varda.
Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”