< Jesaja 61 >
1 Herrans, Herrans Ande är med mig, derföre hafver Herren smort mig; han hafver sändt mig till att predika dem eländom, till att förbinda de förkrossada hjerta, till att predika de fångar förlossning, och dem bundnom öppning;
Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
2 Till att predika ett nådeligit Herrans år, och en vår Guds hämndadag, till att hugsvala alla sörjande.
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
3 Till att skaffa dem sörjandom i Zion, att dem skall prydning för asko, glädjeolja för sorg, och skön kläder för en bedröfvad anda gifven varda, att de skola kallas rättfärdighetenes trä, Herrans plantering till pris.
àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
4 De skola uppbygga de gamla öden, och låta uppkomma det i förtiden förstördt är; de skola förnya de öde städer, som ifrå slägte till slägte hafva förstörde legat.
Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
5 Främmande skola stå och föda edra hjordar, och utländningar skola vara edra åkermän och vingårdsmän.
Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
6 Men I skolen heta Herrans Prester, och man skall kalla eder vår Guds tjenare; och skolen äta Hedningarnes ägodelar, och berömma eder af deras härlighet.
A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
7 För edor försmädelse skall dubbelt komma, och för skammena skola de på deras åker glade vara; ty de skola dubbelt äga i deras land; eviga glädje skola de hafva.
Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
8 Ty jag är Herren, som rätten älskar, och hatar rofs bränneoffer; och jag vill skaffa, att deras arbete icke skall förtappadt vara, och ett evigt förbund vill jag göra med dem.
“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
9 Och man skall känna deras säd ibland Hedningarna, och deras efterkommande ibland folken; så att den der ser dem, skall känna dem, att de en säd äro som välsignad är af Herranom.
A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
10 Jag fröjdar mig i Herranom, och min själ är glad i minom Gud; ty han hafver mig utiklädt med salighetenes kläder, och dragit uppå mig rättfärdighetenes kjortel, såsom en brudgumme i sitt prål, såsom en Prest i sin prydning, och såsom en brud hofverar uti sin skrud.
Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
11 Ty såsom frukten växer utu jordene, och fröet uppgår i örtagårdenom; alltså skall rättfärdighet och lof uppgå för alla Hedningar af Herranom Herranom.
Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.