< Jesaja 42 >
1 Si min Tjenare, jag uppehåller honom, och min utkorade, i hvilkom min själ väl behagar. Jag hafver gifvit honom min Anda; han skall låta komma rätt ibland Hedningarna.
“Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró, àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀; Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀ òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Han skall icke skria eller ropa, och hans röst skall man icke höra på gatomen.
Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe sókè, tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ sókè ní òpópónà.
3 En förbråkad rö skall han icke sönderbryta, och en rykande veka skall han icke utsläcka. Han skall lära hålla rätten i sanning.
Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́, àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa. Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;
4 Han skall icke vara knorrisk eller grufvelig, på det han skall sätta rätt på jordene; och öarna skola vänta efter hans lag.
òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì títí tí yóò fi fi ìdájọ́ múlẹ̀ ní ayé. Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètí wọn sí.”
5 Så säger Herren Gud, som himmelen skapar och utsträcker, den som jordena gör med det deruppå växer; den som folkena, som deruppå är, gifver lif, och anda dem som gå deruppå:
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde, tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn, Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:
6 Jag Herren hafver kallat dig i rättfärdighet, och fattat dig vid handena, och bevarat dig, och hafver gifvit dig till ett förbund i folkena, Hedningomen till ett ljus;
“Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo, Èmi yóò di ọwọ́ rẹ mú. Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn àti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà
7 Att du skall öppna de blindas ögon, och föra fångarna utu fängelse, och de som sitta i mörkret utu fångahuset.
láti la àwọn ojú tí ó fọ́, láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbú àti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n àwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.
8 Jag Herren, det är mitt Namn; och jag skall icke gifva mina äro enom androm, ej heller mitt lof afgudomen.
“Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí! Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn tàbí ìyìn mi fún ère òrìṣà.
9 Si, hvad komma skall förkunnar jag framföreåt, och förkunnar ny ting; förr än det sker, låter jag eder det höra.
Kíyèsi i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé, àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé; kí wọn tó hù jáde mo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”
10 Sjunger Herranom en ny viso, hans lof är intill verldenes ändar; de som i hafvet fara, och hvad deruti är; öarna, och de som der bo.
Kọ orin tuntun sí Olúwa ìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá, ẹ̀yin tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú Òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú wọn.
11 Roper högt, I öken och städer deruti, samt med de byar der Kedar bor; sig fröjde de som bo på klippomen, och rope utaf bergshöjdene.
Jẹ́ kí aginjù àti àwọn ìlú rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn sókè; jẹ́ kí ibùdó ti àwọn ìlú Kedari ń gbé máa yọ̀. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Sela kọrin fún ayọ̀; jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.
12 Låter dem gifva Herranom ärona, och förkunna hans lof på öarna.
Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwa àti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.
13 Herren varder utdragandes såsom en rese; han skall uppväcka nit såsom en krigsman; han skall fröjda sig, och ett gny göra; han skall sinom fiendom öfverhändig blifva.
Olúwa yóò rìn jáde gẹ́gẹ́ bí i ọkùnrin alágbára, yóò ru owú sókè bí ológun; yóò kígbe nítòótọ́, òun yóò ké igbe ogun, òun yóò sì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá rẹ̀.
14 Jag tiger väl till en tid, och är stilla och håller mig; men nu vill jag ropa såsom en barnföderska; jag skall föröda och uppsvälja dem alla.
“Fún ìgbà pípẹ́ ni mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́, mo ti wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, mo sì kó ara ró. Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí, mo sọkún, mo sì ń mí hẹlẹ hẹlẹ.
15 Jag skall föröda berg och högar, och borttorka allt deras gräs; och skall göra vattuströmmarna till öar, och uttorka sjöarna.
Èmi yóò sọ òkè ńlá àti kékeré di ahoro tí n ó sì gbẹ gbogbo ewéko rẹ̀ dànù, Èmi yóò sọ àwọn odò di erékùṣù n ó sì gbẹ àwọn adágún.
16 Men de blinda vill jag leda på den vägen, som de icke veta; Jag vill föra dem på de stigar, som de icke känna; jag vill sätta mörkret för dem till ett ljus, och det oslätt är, till jemnhet; detta vill jag göra dem, och icke öfvergifva dem.
Èmi yóò tọ àwọn afọ́jú ní ọ̀nà tí wọn kò tí ì mọ̀, ní ipa ọ̀nà tí ó ṣàjèjì sí wọn ni èmi yóò tọ́ wọn lọ; Èmi yóò sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn àti ibi pálapàla ni èmi ó sọ di kíkúnná. Àwọn nǹkan tí máa ṣe nìyìí; Èmi kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
17 Men de som förlåta sig på afgudar, och säga till gjuten beläte: I ären våre gudar; de skola tillbakavända, och till skam varda.
Ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé òrìṣà, tí wọ́n wí fún ère pé, ‘Ẹ̀yin ni Ọlọ́run wa,’ ni a ó dá padà pẹ̀lú ìtìjú.
18 Hörer, I döfve, och ser härtill, I blinde, att I mågen se.
“Gbọ́, ìwọ adití, wò ó, ìwọ afọ́jú, o sì rí!
19 Ho är så blind som min tjenare? Och ho är så döf som mitt bådskap, den jag sänder? Ho är så blind som den fullkomlige, och så blind såsom Herrans tjenare?
Ta ló fọ́jú bí kò ṣe ìránṣẹ́ mi, àti odi gẹ́gẹ́ bí oníṣẹ́ tí mo rán? Ta ni ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a fi jìnmí, ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Olúwa?
20 Man predikar väl mycket, men de hållat intet; man säger dem nog, men de vilja icke hörat.
Ẹ̀yin ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan, ṣùgbọ́n ẹ kò ṣe àkíyèsí; etí yín yà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́ nǹkan kan.”
21 Likväl vill Herren dem godt, för sina rättfärdighets skull, och att han skall göra sin lag härlig och stor.
Ó dùn mọ́ Olúwa nítorí òdodo rẹ̀ láti mú òfin rẹ lágbára àti ògo.
22 Det är ett bedröfvadt och skinnadt folk; de äro allesammans besnärde uti kulor, och bortgömde i fångahus; de äro vordne till rof, och ingen hjelpare är; beskinnade, och ingen är, som säger: Få dem igen.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan nìyìí tí a jà lógun tí a sì kó lẹ́rú, gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun, tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n. Wọ́n ti di ìkógun, láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀; wọ́n ti di ìkógun, láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”
23 Hvilken är ibland eder, som aktar härtill; märker, och hörer hvad härefter kommer.
Ta ni nínú yín tí yóò tẹ́tí sí èyí tàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?
24 Ho hafver öfvergifvit Jacob till sköfvels, och Israel röfvarom? Hafver icke Herren gjort det, emot hvilkom vi syndat hafve? Och de ville icke vandra på hans vägar, och lydde icke hans lag.
Ta ni ó fi Jakọbu lélẹ̀ fún ìkógun, àti Israẹli sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí? Kì í ha ṣe Olúwa ni, ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí? Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀; wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.
25 Derföre hafver han utskuddat öfver dem sina vredes grymhet, och en krigsmagt, och hafver upptändt dem allt omkring; men de aktade det intet. Han fängde uppå dem, men de lade det intet uppå hjertat.
Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí, rògbòdìyàn ogun. Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀ èdè kò yé wọn; ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.