< Jesaja 40 >
1 Tröster, tröstar mitt folk, säger edar Gud;
Ẹ tù ú nínú, ẹ tu ènìyàn mi nínú, ni Ọlọ́run yín wí.
2 Taler ljufliga med Jerusalem, och prediker för thy, att dess tid är fullbordad; ty dess missgerning är förlåten; ty det hafver fångit dubbelt af Herrans hand för alla sina synder.
Sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ fún Jerusalẹmu kí o sì kéde fún un pé iṣẹ́ àṣekára rẹ̀ ti parí, pé à ti san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, pé ó ti rí i gbà láti ọwọ́ Olúwa ìlọ́po méjì fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
3 Ens Predikares röst är i öknene: Bereder Herranom väg, görer en jemnan stig på markene vårom Gudi.
Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù: “Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ṣe òpópó tí ó tọ́ ní aginjù fún Ọlọ́run wa.
4 Alle dalar skola upphöjde varda, och all berg och högar skola förnedrade varda, och det ojemnt är skall jemnas, och det oslätt är skall slätt varda.
Gbogbo àfonífojì ni a ó gbé sókè, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀; wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àti ọ̀nà pálapàla ni a óò sọ di títẹ́jú pẹrẹsẹ.
5 Ty Herrans härlighet skall uppenbarad varda; och allt kött skall tillsammans se, att Herrans mun talar.
Ògo Olúwa yóò sì di mí mọ̀, gbogbo ènìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rí i. Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”
6 En röst säger: Predika. Och han sade: Hvad skall jag predika? Allt kött är hö, och all dess godhet är såsom ett blomster i markene.
Ohùn kan wí pé, “Kígbe sókè.” Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?” “Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko, àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná igbó.
7 Höet torkas bort, blomstret förvissnar; ty Herrans ande blås derin; ja, folket är höet.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n. Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.
8 Höet torkas bort, blomstret förvissnar; men vår Guds ord blifver evinnerliga.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”
9 Zion, du som predikar, stig upp på ett högt berg; Jerusalem, du som predikar, häf upp dina röst med magt. Häf upp, och frukta dig intet; säg Juda städer: Si, der är edar Gud.
Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Sioni, lọ sí orí òkè gíga. Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jerusalẹmu, gbé ohùn rẹ sókè pẹ̀lú ariwo, gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù; sọ fún àwọn ìlú u Juda, “Ọlọ́run rẹ nìyìí!”
10 Ty si, Herren, Herren kommer väldeliga, och hans arm skall varda rådandes. Si, hans arbete och hans gerning skall icke varda utan frukt.
Wò ó, Olúwa Olódùmarè náà ń bọ̀ wá pẹ̀lú agbára, apá rẹ̀ sì ń jẹ ọba fún un. Wò ó, èrè rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀, àti ìdápadà rẹ̀ tí ń bá a bọ̀ wá.
11 Han skall föda sin hjord såsom en herde; han skall församla lamben i sin famn, och bära dem i sitt sköt, och fordra de lambdigra.
Ó ń tọ́ àwọn agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn: Ó kó àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ní apá rẹ̀. Ó sì gbé wọn súnmọ́ oókan àyà rẹ̀; ó sì fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ darí àwọn tí ó ní.
12 Ho mäter vattnet med handene, och fattar himmelen med sin spann, och begriper jordena med tre fingers mått, och väger bergen med en vigt, och högarna med en våg?
Ta ni ó tiwọn omi nínú kòtò ọwọ́ rẹ̀, tàbí pẹ̀lú ìbú ọwọ́ rẹ̀ tí ó wọn àwọn ọ̀run? Ta ni ó ti kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé jọ nínú apẹ̀rẹ̀, tàbí kí ó wọn àwọn òkè ńlá lórí ìwọ̀n àti òkè kéékèèké nínú òsùwọ̀n?
13 Ho undervisar Herrans Anda; och hvad rådgifvare lärer honom?
Ta ni ó ti mọ ọkàn Olúwa, tàbí tí ó ti tọ́ ọ ṣọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
14 Hvem frågar han om råd, den honom förstånd gifver, och lärer honom rättsens väg, och lärer honom klokhet, och viser honom förståndsens väg?
Ta ni Olúwa ké sí kí ó là á lọ́yẹ àti ta ni ó kọ́ òun ní ọ̀nà tí ó tọ́? Ta ni ẹni náà tí ó kọ́ ọ ní ọgbọ́n tàbí tí ó fi ipa ọ̀nà òye hàn án?
15 Si, Hedningarna äro aktade såsom en droppe den uti ämbaret blifver, och såsom ett grand det i vågskålene blifver. Si, öarna äro såsom ett litet stoft.
Nítòótọ́ àwọn orílẹ̀-èdè dàbí i ẹ̀kún omi nínú garawa; a kà wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí eruku lórí ìwọ̀n; ó wọn àwọn erékùṣù àfi bí eruku múnúmúnú ni wọ́n.
16 Libanon vore allt för litet till eld, och dess djur allt för få till bränneoffer.
Lebanoni kò tó fún pẹpẹ iná, tàbí kí àwọn ẹranko rẹ̀ kí ó tó fún ẹbọ sísun.
17 Alle Hedningar äro intet för honom, och såsom platt intet aktade.
Níwájú rẹ̀ ni gbogbo orílẹ̀-èdè dàbí ohun tí kò sí; gbogbo wọn ló kà sí ohun tí kò wúlò tí kò tó ohun tí kò sí.
18 Vid hvem viljen I då likna Gud? Eller hvad viljen I göra honom för en liknelse?
Ta ni nígbà náà tí ìwọ yóò fi Ọlọ́run wé? Ère wo ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé rẹ̀?
19 En mästare gjuter väl ett beläte, och guldsmeden förgyller det, och gör silfkedjor deruppå.
Ní ti ère, oníṣọ̀nà ni ó dà á, ti alágbẹ̀dẹ wúrà sì fi wúrà bò ó tí a sì ṣe ẹ̀wọ̀n ọ̀nà sílífà fún un.
20 Sammalunda, den ett armt häfoffer förmår, han utväljer ett trä, som icke förruttnar, och söker en klok mästare dertill, den ett beläte bereder, som blifver beståndandes.
Ọkùnrin kan tí ó tálákà jù kí ó lè mú irú ọrẹ bẹ́ẹ̀ wá, wá igi tí kò le è rà. Ó wá oníṣọ̀nà tí ó láti ṣe àgbékalẹ̀ ère tí kì yóò le è ṣubú.
21 Veten I intet? Hören I intet? Är detta icke kungjordt eder tillförene? Hafven I icke förstått det af jordenes begynnelse?
Ǹjẹ́ o kò tí ì mọ̀ ìwọ kò tí ì gbọ́? A kò tí ì sọ fún ọ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá? Ìwọ kò tí ì mọ láti ìgbà ìpìlẹ̀ ayé?
22 Han sitter öfver jordenes krets, och de som bo deruppå äro såsom gräshoppor; den der himmelen uttänjer såsom ett tunnt skinn, och utsträcker det såsom ett tjäll, der man bor uti;
Òun jókòó lórí ìtẹ́ ní òkè òbírí ilẹ̀ ayé, àwọn ènìyàn rẹ̀ sì dàbí i láńtata. Ó ta àwọn ọ̀run bí ìbòrí ìgúnwà, ó sì nà wọ́n jáde gẹ́gẹ́ bí àgọ́ láti gbé.
23 Den der Förstarna omintetgör, och domarena på jordene förlägger;
Ó sọ àwọn ọmọ ọba di asán àti àwọn aláṣẹ ayé yìí ni ó ti sọ dòfo.
24 Lika som deras slägte hvarken hade plantering eller säd, eller rot i jordene; så att de borttorkas, när ett väder blås på dem, och en väderflaga förer dem bort, såsom agnar.
Gẹ́rẹ́ tí a ti gbìn wọ́n, kété tí a gbìn wọ́n, kété tí wọ́n fi gbòǹgbò múlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó fẹ́ atẹ́gùn lù wọ́n gbogbo wọn sì gbẹ, bẹ́ ni ìjì líle sì gbá wọn lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò.
25 Vid hvem viljen I då likna mig, den jag lik är? säger den Helige.
“Ta ni ẹ ó fi mi wé? Tàbí ta ni ó bá mi dọ́gba?” ni Ẹni Mímọ́ wí.
26 Upplyfter edor ögon i höjdena, och ser; ho hafver de ting skapat, och förer deras här fram efter tal? Den som kallar dem alla vid namn. Hans förmåga och starka kraft är så stor, att honom icke ett fela kan.
Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wo àwọn ọ̀run. Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí? Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kan tí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan. Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀, ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn kò sọnù.
27 Hvi säger du då, Jacob, och du, Israel, talar: Min väg är Herranom fördold, och min rätt går framom min Gud?
Èéṣe tí o fi sọ, ìwọ Jakọbu? Àti tí o ṣàròyé, ìwọ Israẹli, “Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa; ìṣe mi ni a kò kọbi ara sí láti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?
28 Vetst du icke? Hafver du icke hört? Herren, den evige Gud, som jordenes ändar skapat hafver, varder hvarken trött eller mödd. Hans förstånd är oransakeligit.
Ìwọ kò tí ì mọ̀? Ìwọ kò tí ì gbọ́? Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé, Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé. Agara kì yóò da bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣàárẹ̀, àti òye rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdínwọ̀n rẹ̀.
29 Han gifver dem trötta kraft, och dem magtlösom starkhet nog.
Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀ ó sì fi kún agbára àwọn tí agara dá.
30 De ynglingar varda trötte, och uppgifvas, och de kanske män falla;
Àní, ó ń rẹ̀ wọ́n àwọn ọ̀dọ́, wọ́n ń rẹ̀wẹ̀sì, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì ń kọsẹ̀ wọ́n ṣubú;
31 Men de som vänta efter Herran, de få en ny kraft, så att de skola uppfara med vingar såsom örnar; de skola löpa, och icke uppgifvas; de skola vandra, och icke trötte varda.
ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sọ agbára wọn di ọ̀tun. Wọn yóò fìyẹ́ fò lókè bí idì; wọn yóò sáré àárẹ̀ kò ní mú wọn, wọn yóò rìn òòyì kò ní kọ́ wọn.