< 1 Mosebok 46 >

1 Israel for dit med allt det honom tillhörde. Och då han kom till BerSaba, offrade han ett offer sins faders Isaacs Gudi.
Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
2 Och Gud sade till honom om nattena i ene syn: Jacob, Jacob. Han sade: Här är jag.
Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
3 Och han sade: Jag är Gud, dins faders Gud, frukta dig icke att fara in i Egypten; förty, der vill jag göra dig till ett mägtigt folk.
Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
4 Jag vill fara dit med dig, och vill åter föra dig derut. Och Joseph skall lägga sina hand uppå din ögon.
Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
5 Då for Jacob ifrå BerSaba. Och Israels barn förde Jacob sin fader, med sin barn och hustrur, på vagnomen, som Pharao hade sändt till att föra dem med.
Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
6 Och togo sin boskap och håfvor, som de förvärfvat hade i Canaans lande, och kommo så in uti Egypten, Jacob och all hans säd med honom:
Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
7 Hans barn och hans barnabarn med honom, hans döttrar, och hans barns döttrar, och all hans säd.
Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
8 Desse äro Israels barns namn, de som kommo i Egypten: Jacob och hans söner. Jacobs förstfödde son Ruben.
Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
9 Rubens barn: Hanoch, Pallu, Hezron och Charmi.
Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
10 Simeons barn: Jemuel, Jamin, Ohad, Jachin, Zohar, och Saul den Cananeiske qvinnones son.
Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
11 Levi barn: Gerson, Kehat och Merari.
Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
12 Juda barn: Er, Onan, Sela, Perez och Serah. Men Er och Onan dödde i Canaans lande. Men Perez barn: Hezron och Hamul.
Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
13 Isaschars barn: Thola, Phuva, Job och Simron.
Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
14 Sebulons barn: Sered, Elon och Jahleel.
Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
15 Desse äro barnen af Lea, som hon födde Jacob i Mesopotamien, med sine dotter Dina: De göra tillhopa alle, med söner och döttrar, tre och tretio själar.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
16 Gads barn: Ziphion, Haggi, Suni, Ezbon, Eri, Arodi och Areli.
Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
17 Assers barn: Jimna, Jisua, Jisui, Brya; och Serah, deras syster. Men Bryas barn: Heber och Malchiel.
Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
18 Desse äro Silpas barn, som Laban gaf Lea sine dotter, och födde Jacob dessa sexton själar.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
19 Rachels Jacobs hustrus barn: Joseph och BenJamin.
Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
20 Och Joseph vordo födde i Egypten, Manasse och Ephraim, som honom födde Asnath Potiphera dotter Prestens i On.
Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
21 BenJamins barn: Bela, Becher, Asbel, Gera, Naaman, Ehi, Ros, Muppim, Huppim och Ard.
Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
22 Desse äro barnen af Rachel, som Jacob födde äro; alle tillhopa fjorton själar.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
23 Dans barn: Husim.
Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
24 Naphthali barn: Jahzeel, Guni, Jezer och Sillem.
Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
25 Desse äro Bilhas barn, som Laban hade gifvit sine dotter Rachel, och födde Jacob dessa sju själar.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
26 Alla själar som kommo med Jacob in i Egypten, som utgångne voro af hans länd, undantagande hans barnahustrur, äro alle tillsamman sex och sextio själar.
Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
27 Och Josephs barn, som honom vordo födde i Egypten, voro två själar: Så att alla Jacobs hus själar, som kommo in i Egypten, voro sjutio.
Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
28 Och han sände Juda för sig till Joseph, att han skulle visa honom vägen till Gosen; och de kommo in i landet Gosen.
Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
29 Då spände Joseph före sin vagn, och for ut emot Israel sin fader till Gosen. Och då han fick se honom, föll han om hans hals, och gret svårliga på hans hals.
Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
30 Då sade Israel till Joseph: Nu vill jag gerna dö, efter det jag hafver sett ditt ansigte, att du ännu lefver.
Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
31 Joseph sade till sina bröder och sin faders hus: Jag vill fara upp, och undervisa der Pharao, och säga till honom: Mine broder och mins faders hus är kommit till mig utaf Canaans land;
Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
32 Och äro herdar, ty det är sådana folk, som med boskap umgå plägar; deras får och fä, och allt det de hafva, hafva de fört med sig.
Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
33 Då nu Pharao varder eder kallandes, och säger: Hvad är edar handel?
Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
34 Så skolen I säga: Dine tjenare äro folk, som med boskap umgå ifrå vår barndom allt härtill, både vi och våre fäder, på det I må få bo i det landet Gosen; förty alle herdar äro såsom en styggelse för de Egyptier.
ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”

< 1 Mosebok 46 >