< 1 Mosebok 34 >
1 Men Dina Leas dotter, den hon Jacob födt hade, gick ut till att bese dess landsens döttrar.
Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
2 Då Sichem, Hemors Heveens son, som var dess landsens herre, såg henne, tog han henne, och belägrade henne, och förkränkte henne.
Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
3 Och hon låg honom hårdt på hjertat, och han hade pigona kära, och talade ljufliga med henne.
Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
4 Och Sichem sade till sin fader Hemor: Tag mig den pigona till hustru.
Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
5 Och Jacob förnam, att hans dotter Dina var skämd, och hans söner voro med boskapenom ute på markene: Och Jacob tigde till dess de kommo.
Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
6 Då gick Hemor Sichems fader ut till Jacob, till att tala med honom.
Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
7 I det kommo Jacobs söner af markene; och då de det hörde, förtröt det männerna, och vordo ganska vrede, att han hade gjort en dårskap i Israel, och belägrat Jacobs dotter; ty det var icke rätt gjordt.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
8 Då talade Hemor med dem, och sade: Mins sons Sichems hjerta trängtar efter edra dotter; käre, gifver honom henne till hustru.
Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
9 Befrynder eder med oss; gifver oss edra döttrar, och tager I våra döttrar.
Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
10 Och bor när oss: Landet skall stå eder öppet; bygger och bruker, och bor derinne.
Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
11 Och Sichem sade till hennes fader och bröder: Låter mig finna nåd när eder, hvad I mig sägen, det vill jag gifva.
Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
12 Begärer man troliga af mig morgongåfvor och skänker, jag vill gifva, som I begären; gifver mig allenast pigona till hustru.
Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
13 Då svarade Jacobs söner Sichem, och hans fader Hemor, och talade bedrägeliga, derföre, att deras syster Dina var skämd:
Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
14 Och sade till dem: Vi kunne det icke göra, att vi skole gifva våra syster enom oomskornom manne; ty det vore oss en skam.
Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
15 Dock likväl vilje vi vara eder till viljes, om I varden oss like, och allt mankön ibland eder varder omskoret.
Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
16 Då vilje vi gifva eder våra döttrar, och taga oss edra döttrar, och bo när eder, och vara ett folk.
Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
17 Men hvar I icke viljen lyda oss, och omskära eder, så vilje vi taga våra dotter, och fara vår väg.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
18 Det talet behagade Hemer och hans son väl.
Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
19 Och den unge mannen fördröjde intet att göra så; förty han hade lust till Jacobs dotter, och han var härlig hållen öfver alla i hans faders huse.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
20 Så gingo Hemor och hans son Sichem i stadsporten, och talade med borgarena i stadenom, och sade:
Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
21 Desse män äro fridsamme när oss, och vilja bygga och bo i landena. Så är nu landet vidt begripet; vi vilje taga oss deras döttrar, och gifva dem våra döttrar.
Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
22 Men då vilja de vara oss till viljes, så att de bo när oss, och varda ett folk med oss, om vi omskäre allt det som mankön är ibland oss, såsom de omskorne äro.
Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
23 Deras boskap och ägodelar, och allt det de hafva, blifver vårt, om vi eljest blifvom dem till viljes, så att de bo när oss.
Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
24 Och de lydde Hemor och Sichem hans sone, alle de som genom hans stadsport ut och in gingo, och omskoro allt det som mankön var, det som i deras stad ut och in gick.
Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
25 Och på tredje dagenom, då det värkte dem, togo de två Jacobs söner, Simeon och Levi, Dinas bröder, hvardera sitt svärd, och gingo dristeliga in i staden, och slogo ihjäl allt det som var mankön.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
26 Och slogo också ihjäl Hemor och hans son Sichem med svärds ägg, och togo sina syster Dina utaf Sichems huse, och gingo sin väg.
Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
27 Då kommo Jacobs söner öfver de slagna, och skinnade staden, derföre, att de skämt hade deras syster.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
28 Och togo deras får, fä, åsnar, och hvad i stadenom och på markene var:
Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
29 Och alla deras håfvor; all barn och qvinnor togo de till fångar, och skinnade allt det i husen var.
Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
30 Och Jacob sade till Simeon och Levi: I hafven åstadkommit, att jag blifver illa känder för alla dessa lands inbyggare, de Cananeer och Phereseer: Och jag är en ringa hop; när de nu församla sig öfver mig, så slå de mig ihjäl, så varder jag om intet gjord med mino huse.
Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
31 Men de svarade: Skulle de då handla med våra syster, såsom med ene sköko?
Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”