+ 1 Mosebok 1 >
1 I begynnelsen skapade Gud Himmel och Jord.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ohun gbogbo Ọlọ́run dá àwọn ọ̀run àti ayé.
2 Och jorden var öde och tom, och mörker var på djupet, och Guds Ande sväfde öfver vattnet.
Ayé sì wà ní rúdurùdu, ó sì ṣófo, òkùnkùn sì wà lójú ibú omi, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì ń rábàbà lójú omi.
3 Och Gud sade: Varde Ljus, och det vardt Ljus.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà,” ìmọ́lẹ̀ sì wà.
4 Och Gud såg ljuset, att det var godt. Då skilde Gud ljuset ifrå mörkret.
Ọlọ́run rí i pé ìmọ́lẹ̀ náà dára, ó sì ya ìmọ́lẹ̀ náà sọ́tọ̀ kúrò lára òkùnkùn.
5 Och kallade ljuset Dag, och mörkret Natt. Och vardt af afton och morgon den första dagen.
Ọlọ́run sì pe ìmọ́lẹ̀ náà ní “ọ̀sán,” àti òkùnkùn ní “òru.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní.
6 Och Gud sade: Varde ett Fäste emellan vattnen, och åtskilje vatten ifrå vatten.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí òfúrufú kí ó wà ní àárín àwọn omi, láti pààlà sí àárín àwọn omi.”
7 Och Gud gjorde fästet, och åtskilde det vattnet, som var under fästet, ifrå det vatten, som var ofvan fästet. Och det skedde så.
Ọlọ́run sì dá òfúrufú láti ya omi tí ó wà ní òkè òfúrufú kúrò lára omi tí ó wà ní orí ilẹ̀. Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
8 Och Gud kallade fästet Himmel. Och vardt af afton och morgon den andra dagen.
Ọlọ́run sì pe òfúrufú ní “ọ̀run.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kejì.
9 Och Gud sade: Församle sig vattnet, som är under himmelen, uti besynnerligit rum, att det torra må synas. Och det skedde så.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi abẹ́ ọ̀run wọ́ papọ̀ sí ojú kan, kí ilẹ̀ gbígbẹ sì farahàn.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
10 Och Gud kallade det torra Jord, och vattnens församlingar kallade han Haf. Och Gud såg, att det var godt.
Ọlọ́run sì pe ilẹ̀ gbígbẹ náà ní “ilẹ̀,” àti àpapọ̀ omi ní “òkun.” Ọlọ́run sì rí i wí pé ó dára.
11 Och Gud sade: Bäre jorden gräs och örter, som frö hafva, och fruktsam trä, att hvart och ett bär frukt efter sin art, och hafver sitt eget frö i sig sjelfvo på jordene. Och det skedde så.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó hu ọ̀gbìn: ewéko ti yóò máa mú èso wá àti igi tí yóò máa so èso ní irú tirẹ̀, tí ó ní irúgbìn nínú.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
12 Och jorden bar gräs och örter, som frö hade, hvart efter sin art, och trä, som frukt båro, och hade sitt eget frö i sig sjelfvo, hvart efter sin art. Och Gud såg, att det var godt.
Ilẹ̀ sì hù ọ̀gbìn: ewéko tí ó ń so èso ní irú tirẹ̀, àti igi tí ń so èso, tí ó ní irúgbìn nínú ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì ri pé ó dára.
13 Och vardt af afton och morgon den tredje dagen.
Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹta.
14 Och Gud sade: Varde Ljus uti himmelens fäste, och åtskilje dag och natt, och gifve tecken, månader, dagar och år.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà ní ojú ọ̀run, láti pààlà sí àárín ọ̀sán àti òru, kí wọn ó sì máa wà fún àmì láti mọ àwọn àsìkò, àti àwọn ọjọ́ àti àwọn ọdún.
15 Och vare för ljus uti himmelens fäste, och lyse på jordene. Och det skedde så.
Kí wọn ó jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ní ojú ọ̀run láti tan ìmọ́lẹ̀ sí orí ilẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
16 Och Gud gjorde tu stor ljus; ett stort ljus, som regerade dagen, och ett litet ljus, som regerade nattena; och stjernor.
Ọlọ́run dá ìmọ́lẹ̀ ńlá ńlá méjì, ìmọ́lẹ̀ tí ó tóbi láti ṣe àkóso ọ̀sán àti ìmọ́lẹ̀ tí ó kéré láti ṣe àkóso òru. Ó sì dá àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú.
17 Och Gud satte dem uti himmelens fäste, att de skina skulle på jordena;
Ọlọ́run sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ sí ojú ọ̀run láti máa tan ìmọ́lẹ̀ si orí ilẹ̀,
18 Och regera dagen och nattena, och åtskilja ljuset och mörkret. Och Gud såg, att det var godt.
láti ṣàkóso ọ̀sán àti òru àti láti pààlà sí àárín ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
19 Och vardt af afton och morgon den fjerde dagen.
Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹrin.
20 Och Gud sade: Göre vattnet af sig kräkande och lefvande djur, och foglar, som på jordene flyga under himmelens fäste.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi kí ó kún fún àwọn ohun alààyè, kí àwọn ẹyẹ kí ó sì máa fò ní òfúrufú.”
21 Och Gud skapade stora hvalar, och allahanda lefvande och kräkande djur, som vattnet af sig gör, hvart efter sin art, och allahanda fjäderfoglar, hvart efter sin art. Och Gud såg, att det var godt.
Nítorí náà Ọlọ́run dá àwọn ẹ̀dá alààyè ńlá ńlá sí inú òkun, àwọn ohun ẹlẹ́mìí àti àwọn ohun tí ń rìn ní onírúurú tiwọn, àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́ ní onírúurú tiwọn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
22 Och välsignade dem, och sade: Varer fruktsamme, och förökens, och uppfyller hafsens vatten, och foglarna föröke sig på jordene.
Ọlọ́run súre fún wọn, ó sì wí pé, “Ẹ máa bí sí i, ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ kún inú omi òkun, kí àwọn ẹyẹ náà sì máa pọ̀ sí i ní orí ilẹ̀.”
23 Och vardt af afton och morgon den femte dagen.
Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ karùn-ún.
24 Och Gud sade: Göre jorden af sig lefvande djur, hvart efter sin art, fänad, kräkande djur, och vilddjur på jordene, hvart efter sin art. Och det skedde så.
Ọlọ́run sì wí pé, “Kí ilẹ̀ kí ó mú ohun alààyè jáde ní onírúurú wọn: ẹran ọ̀sìn, àwọn ohun afàyàfà àti àwọn ẹran inú igbó, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní irú tirẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
25 Och Gud gjorde vilddjur på jordene, hvart efter sin art, fänad efter sin art, allahanda kräkande djur på jordene efter sin art. Och Gud såg, att det var godt.
Ọlọ́run sì dá ẹranko inú igbó àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ní irú tirẹ̀ àti gbogbo ohun alààyè tí ń rìn ní ilẹ̀ ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
26 Och Gud sade: Låt oss göra Menniskona till ett beläte, det oss likt är, den råda skall öfver fiskarna i hafvet, och öfver foglarna under himmelen, och öfver fänaden, och öfver hela jordena, och öfver allt det som kräker på jordene.
Lẹ́yìn náà ni Ọlọ́run wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a dá ènìyàn ní àwòrán ara wa, gẹ́gẹ́ bí àwa ti rí, kí wọn kí ó jẹ ọba lórí ẹja òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run, ẹran ọ̀sìn, gbogbo ilẹ̀ àti lórí ohun gbogbo tí ń rìn lórí ilẹ̀.”
27 Och Gud skapade menniskona sig till ett beläte, till Guds beläte skapade han honom, Man och Qvinno skapade han dem.
Nítorí náà, Ọlọ́run dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀, ní àwòrán Ọlọ́run ni ó dá a, akọ àti abo ni ó dá wọn.
28 Och Gud välsignade dem, och sade till dem: Varer fruktsamme, och föröker eder, och uppfyller jordena, och hafver henne under eder, och råder öfver fiskarna i hafvet, och öfver foglarna under himmelen, och öfver all djur, som kräla på jordene.
Ọlọ́run sì súre fún wọn, Ọlọ́run sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ ṣe ìkápá ayé. Ẹ ṣe àkóso àwọn ẹja inú òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó ń rìn ní orí ilẹ̀.”
29 Och Gud sade: Si, jag hafver gifvit eder allahanda örter, som frö hafva på hela jordene, och allahanda fruktsam trä, och trä, som frö hafva i sig sjelfvo, eder till mat.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo fi gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ń so èso fún un yín bí oúnjẹ àti àwọn igi eléso pẹ̀lú. Gbogbo rẹ̀ yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín.
30 Och allom djurom på jordene, och allom foglom under himmelen, och allo thy, som kräker på jordene, och lif hafver, att de skola hafva allahanda gröna örter till att äta. Och det skedde så.
Àti fún àwọn ẹranko inú igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ohun afàyàfà, gbogbo ohun tó ní èémí ìyè nínú ni mo fi ewéko fún bí oúnjẹ.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
31 Och Gud såg på allt det han gjort hade, och si, det var allt ganska godt. Och vardt af afton och morgon den sjette dagen.
Ọlọ́run sì rí àwọn ohun gbogbo tí ó dá, ó dára gidigidi. Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹfà.