< Hesekiel 9 >
1 Och han ropade med höga röst för min öron, och sade: Det är för handene, att staden skall hemsökt varda, och hvar och en hafve ett mordvapen i sine hand.
Mo gbọ́ ti ó kígbe ní ohùn rara pé, “Mú àwọn olùṣọ́ ìlú súnmọ́ itòsí, kí olúkúlùkù wọn mú ohun ìjà olóró lọ́wọ́.”
2 Och si, der kommo sex män på vägen ifrå öfra portenom, som norrut är, och hvar och en hade ett skadeligit vapen i sine hand; men der var en ibland dem, som hade linnkläder uppå, och ett skriftyg vid sina sido, och de gingo in, och trädde intill kopparaltaret.
Lójú ẹsẹ̀ ni ọkùnrin mẹ́fà jáde láti ẹnu-ọ̀nà òkè tó kọjú sí ìhà àríwá, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà olóró lọ́wọ́ wọn. Ọkùnrin kan tó wọ aṣọ funfun gbòò wa láàrín wọn, pẹ̀lú ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Gbogbo wọn sì dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ idẹ.
3 Och Israels Guds härlighet steg upp ifrå Cherub, öfver hvilkom hon var, intill huströskelen, och ropade till honom, som linnkläden på hade, och skriftyget vid sina sido.
Ògo Ọlọ́run Israẹli sì gòkè kúrò lórí kérúbù, níbi tó wà tẹ́lẹ̀ lọ sí ibi ìloro tẹmpili. Nígbà náà ni Olúwa pe ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun náà tí ó sì ní ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
4 Och Herren sade till honom: Gack igenom Jerusalems stad, och teckna de män i ännet med ett tecken, som sucka och jämra sig öfver den styggelse, som derinne sker.
Ó sì sọ fún un pé, “La àárín ìlú Jerusalẹmu já, kí ìwọ sì fi àmì síwájú orí gbogbo àwọn tó ń kẹ́dùn, tó sì ń sọkún nítorí ohun ìríra tí wọn ń ṣe láàrín rẹ̀.”
5 Men till de andra sade han, mig åhörande: Går efter dessom igenom staden, och slår derinne; edor ögon skola ingen skona, eller med någon öfverse.
Bí mo ṣe ń fetí sí èyí, O tún sọ fún àwọn yòókù pé, “Tẹ̀lé ọkùnrin náà lọ sí àárín ìlú láti pa láì dá sí àti láì ṣàánú rárá.
6 Slår både gamla, ynglingar, jungfrur, barn och qvinnor, till döds; men de som tecknet hafva på sig, ingen af dem skolen I vederkomma; begynner först uppå minom helgedom. Och de begynte på de gamla män, som för husena voro.
Ẹ pa arúgbó àti ọ̀dọ́mọkùnrin, ẹ pa ọlọ́mọge, obìnrin àti ọmọ kéékèèké, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn tó ní àmì. Ẹ bẹ̀rẹ̀ láti ibi mímọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà tó wà níwájú tẹmpili.
7 Och han sade till dem: Ohelger huset och görer gårdarna fulla med döda kroppar; går här ut. Och de gingo ut, och slogo i stadenom.
Nígbà náà lo sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ tẹmpili náà di àìmọ́, kí òkú sì kún àgbàlá náà. Ẹ lọ!” Wọ́n jáde síta, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa ènìyàn láàrín ìlú.
8 Och då de utslagit hade, var jag ännu qvar blifven, och jag föll på mitt ansigte, ropade och sade: Ack! Herre Herre, vill du då förgöra alla de qvarlefda i Israel, att du så utgjuter dina vrede öfver Jerusalem?
Èmi nìkan ló ṣẹ́kù nígbà tí wọ́n lọ pa àwọn ènìyàn, mo dójú mi bolẹ̀, mo kígbe pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli nípa dída ìbínú gbígbóná rẹ sórí Jerusalẹmu?”
9 Och han sade till mig: Israels hus och Juda hus missgerning är allt för stor; det är icke annat än öfvervåld och orätt i landena och i stadenom; ty de säga: Herren hafver öfvergifvit landet, och Herren ser oss intet.
Ó dá mi lóhùn pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli àti Juda pọ gidigidi; ilé wọn kún fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àti àìṣòótọ́. Wọ́n ní, ‘Olúwa tí kọ ilẹ̀ náà sílẹ̀; Olúwa kò sì rí wa.’
10 Derföre skall mitt öga ock intet skona, och ingen nåd bevisa; utan jag skall göra med dem, som de förtjent hafva.
Nítorí náà, èmi kò ní wò wọ́n pẹ̀lú àánú, èmi kò sì ní dá wọn sí, ṣùgbọ́n Èmi yóò dá ohun tí wọ́n ti ṣe padà sórí wọn.”
11 Och si, den mannen, som linnkläden uppå hade, och skriftyget vid sina sido, svarade, och sade: Jag hafver gjort såsom du mig budit hafver.
Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, tí ó ní ìwo tàdáwà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ròyìn pé, “Mo ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti pàṣẹ fún mi.”