< Hesekiel 30 >

1 Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
2 Du menniskobarn, prophetera, och säg: Detta säger Herren Herren: Jämrer eder, och säger: Ack! ve den dagen.
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
3 Ty dagen är hardt när; ja, Herrans dag är hardt när, en mörk dag; tiden är för handene, att Hedningarna komma skola;
Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
4 Och svärdet skall komma öfver Egypten, och Ethiopien måste förskräckas, när de slagne uti Egypten falla, och dess folk bortfördt, och dess grundval upprifven varder.
Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
5 Ethiopien, och Libyen, och Lydien, med allahanda folk, och Chub, och de som utaf förbundsens land äro, skola med dem falla genom svärd.
Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
6 Detta säger Herren: Egypti försvarare måste falla, och dess magts högfärd måste förgås; ifrå tornet i Sevene skola de falla genom svärd, säger Herren Herren;
“‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
7 Och skola öde varda, såsom deras öde gränsor, och deras städer öde ligga ibland andra öde städer;
Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
8 Att de skola förnimma, att jag är Herren, då jag gör en eld uti Egypten, så att alle de, som dem hjelpa, skola förderfvade varda.
Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
9 På den tiden skola bådskap draga ut ifrå mig till skepps, till att förskräcka Ethiopien, det nu så säkert är, och en förskräckelse skall vara ibland dem, lika som det gick med Egypten, då dess tid kom; ty si, det kommer visserliga.
“‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
10 Detta säger Herren Herren: Jag skall förminska den myckenhet uti Egypten, genom NebucadNezar, Konungen i Babel.
“‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
11 Ty han och hans folk med honom, samt med Hedningarnas tyranner, äro dertill kallade, att de skola förderfva landet, och skola utdraga sin svärd emot Egypten, så att landet skall allestäds med slagna fullt ligga.
Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
12 Och jag skall uttorka strömmarna, och sälja landet uti arga menniskors händer, och skall föröda landet, och hvad deruti är, genom främmande; jag, Herren, hafver talat det.
Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
13 Detta säger Herren Herren: Jag skall förgöra de beläte i Noph, och göra en ända uppå afgudarna, och Egypten skall ingen Första mer hafva, och skall sända en förskräckelse uti Egypti land.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
14 Jag skall göra Patros öde, och upptända en eld i Zoan, och låta rätten gå öfver No;
Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
15 Och skall utgjuta min grymhet öfver Sin, det Egypti fasthet är, och skall utrota den myckenhet i No.
Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
16 Jag skall upptända en eld uti Egypten, och Sin skall ske ångest och nöd, och No skall nederrifvet varda, och Noph dagliga bedröfvas.
Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
17 De unge män i Aven och PhiBeseth skola falla genom svärd, och qvinnorna fångna bortförda varda.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
18 Thahpanhes skall hafva en mörkan dag, då jag Egypti ok slåendes varder, så att hans magts högfärd skall derinne en ända hafva; han skall med en sky öfvertäckt varda, och hans döttrar skola fångna bortförda varda.
Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
19 Och jag skall låta rätten gå öfver Egypten, att de skola förnimma att jag är Herren.
Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
20 Och det begaf sig i ellofte årena, på sjunde dagen i första månadenom, skedde Herrans ord till mig, och sade:
Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
21 Du menniskobarn, jag skall sönderbryta Pharaos arm, Konungens i Egypten; och si, han skall intet förbunden varda, att han helas må; eller med bandom tillbunden varda, att han må stark blifva, och ett svärd fatta kunna.
“Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
22 Derföre säger Herren Herren alltså: Si, jag vill till Pharao, Konungen i Egypten, och skall bryta hans armar sönder, både den starka och den svaga, att svärdet skall falla honom utu hans hand;
Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
23 Och skall förströ de Egyptier ibland Hedningarna, och förjaga dem i landen.
Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
24 Men Konungens armar af Babel vill jag stärka, och gifva honom mitt svärd i hans hand; och skall bryta Pharaos armar sönder, så att han för honom stånka skall, lika som en den till döds sår är.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
25 Ja, jag vill stärka Konungens armar af Babel, på det Pharaos armar skola sönderbråkade varda; att de skola veta att jag är Herren, när jag gifver Konungenom af Babel svärdet i handena, att han det öfver Egypti land utdraga skall;
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
26 Och jag förströr de Egyptier ibland Hedningarna, och förjagar dem i landen, att de skola förnimma att jag är Herren.
Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

< Hesekiel 30 >