< Hesekiel 13 >
1 Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Du menniskobarn, prophetera emot Israels Propheter, och säg till dem som utaf sitt eget hjerta prophetera: Hörer Herrans ord.
“Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
3 Detta säger Herren Herren: Ve dem galna Prophetomen, som sin egen anda följa, och hafva dock ingen syn.
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
4 O Israel! dine Propheter äro lika som räfvar i öknene.
Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
5 De träda icke framför gapet, och göra sig icke till en mur omkring Israels hus, och stå intet i stridene på Herrans dag.
Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
6 Deras syner äro intet, och deras Prophetie är icke utan lögn; de säga: Herren hafver det sagt; ändock Herren hafver intet sändt dem, och vinnlägga sig, att de kunna hålla sin ord vid magt.
Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
7 Äro icke edra syner intet, och edor Prophetie alltsammans lögn? Och I sägen likväl: Herren hafver det sagt; ändock jag det intet sagt hafver.
Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
8 Derföre säger Herren Herren alltså: Efter I prediken det, der intet af varder, och propheteren lögn, så vill jag till eder, säger Herren Herren.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Och min hand skall komma öfver de Propheter, som predika det, der intet utaf varder, och prophetera lögn; de skola intet vara uti mins folks församling, och uti Israels hus tal icke beskrefne varda, eller komma uti Israels land; och I skolen förnimma, att jag är Herren Herren;
Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
10 Derföre, att de förföra mitt folk, och säga: Frid, ändock der är ingen frid; folket bygger upp väggena; men de bestryka henne med lös kalk.
“‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
11 Säg till de bestrykare, som med lösom kalk bestryka, att det varder affallandes; ty ett slagregn varder kommandes, och stort hagel fallandes, och en väderhvirfvel skall storma deruppå.
nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
12 Si, så skall väggen falla; hvad gäller, man varder då till eder sägandes: Hvar är nu den bestrykningen, som I strukit hafven?
Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
13 Detta säger Herren Herren: Jag skall låta storma en väderhvirfvel i mine grymhet, och ett slagregn i mine vrede, och stora hagelstenar i barm, de skola allt omkullslå.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
14 Och så skall jag omkullslå väggena, den I med lös kalk bestrukit hafven, och kasta henne till jordena, så att man skall se hennes grundval, att hon nedre ligger; och I skolen också derinne förgås, och förnimma att jag är Herren.
Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
15 Alltså skall jag fullkomna mina grymhet på väggene, och uppå dem som henne med lösom kalk bestryka, och säga till eder: Här är hvarken vägg eller bestrykare.
Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
16 Detta äro Israels Propheter, som till Jerusalem prophetera, och predika om frid, ändock der ingen frid är, säger Herren Herren.
Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
17 Och du menniskobarn, ställ ditt ansigte emot döttrarna i ditt folk, hvilka prophetera utaf sitt hjerta; och prophetera emot dem,
“Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
18 Och säg: Detta säger Herren Herren: Ve eder, som gören menniskomen hyende under armarna, och örnagott under hufvuden, både ungom och gamlom, till att fånga själar; när I nu hafven fångat själarna i mitt folk, så sägen I dem lif till;
wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
19 Och ohelgen mig i mitt folk, för en hand full med bjugg, och för en beta bröd, dermed att I dömen de själar till döds, som dock intet dö skulle, och dömen dem till lifs, som dock icke lefva skulle, genom edra lögn ibland mitt folk, som lögn gerna hörer.
Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
20 Derföre säger Herren Herren: Si, jag vill till edor hyende, der I själarna med gripen och förtrösten, och skall rycka dem bort undan edra armar, och de själar, som I gripen och förtrösten, lösa göra;
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
21 Och skall sönderrifva edor örnagott, och fria mitt folk utur edra hand, att I intet mer skolen gripa dem; och I skolen förnimma, att jag; är Herren;
Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
22 Derföre, att I falskeliga bedröfven de rättfärdigas hjerta, hvilka jag intet bedröfvat hafver, och hafven styrkt de ogudaktigas händer, så att de intet omvända sig ifrå sitt onda väsende, på det de måtte lefvande blifva.
Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
23 Derföre skolen I intet mer predika onyttiga läro, eller prophetera; utan jag skall fria mitt folk utur edra händer, och I skolen förnimma, att jag är Herren.
nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”