< 2 Mosebok 31 >
1 Och Herren talade med Mose, och sade:
Olúwa wí fún Mose pé,
2 Si, jag hafver vid namn kallat Bezaleel, Uri son, Hurs sons, af Juda slägte;
“Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
3 Och hafver fyllt honom med Guds Anda; med vishet och förstånd, och konst, och med allahanda verk;
Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
4 Konsteliga till att arbeta på guld, silfver, koppar;
Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
5 Konsteliga utskära och insätta stenar, och konsteliga timbra på trä; till att göra allahanda verk.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
6 Och si, jag hafver fått honom till hjelp Aholiab, Ahisamachs son, af Dans slägte; och hafver hvarjom och enom visom gifvit visdom i hjertat, att de göra skola allt det jag dig budit hafver:
Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
7 Vittnesbördsens tabernakel, vittnesbördsens ark, nådastolen deruppå, och all tabernaklens tyg;
“àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
8 Bordet och dess tyg; den sköna ljusastakan och all hans tyg; rökaltaret;
tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
9 Bränneoffersaltaret med all sin tyg; tvättekaret med sinom fot;
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
10 Ämbetskläden, och de helga kläden Prestens Aarons, och hans söners kläder, till att tjena i Presterskapena;
àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
11 Smörjooljona och rökverk af speceri till helgedomen. Allt det jag hafver budit dig, skola de göra.
òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
12 Och Herren talade med Mose, och sade:
Olúwa wí fún Mose pé,
13 Tala till Israels barn, och säg: Håller min Sabbath; ty han är ett tecken emellan mig och eder, intill edra efterkommande, att I skolen veta, att jag är Herren, den eder helgar.
“Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
14 Derföre håller min Sabbath; ty han skall vara eder helig. Den som ohelgar honom, han skall döden dö; den som gör något arbete på honom, hans själ skall utrotad varda utu hans folk.
“‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
15 Sex dagar skall man arbeta; men på sjunde dagen är Sabbath, Herrans helga hvila. Den som något arbete gör på Sabbathsdagen, han skall döden dö.
Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
16 Derföre skola Israels barn hålla Sabbath, att de med deras efterkommande hålla honom till ett evigt förbund.
Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
17 Han är ett evigt tecken emellan mig och Israels barn. Ty i sex dagar gjorde Herren himmel och jord, men på sjunde dagen höll han upp, och hvilte sig.
Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
18 Och då han hade uttalat med Mose på Sinai berg, gaf han honom två vittnesbördsens taflor; de voro af sten, och skrifna med Guds finger.
Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.