< 5 Mosebok 4 >

1 Och nu hör, Israel, de bud och rätter, som jag eder lärer, att I dem göra skolen, på det I män lefva, och inkomma, och intaga landet, som Herren edra fäders Gud eder gifver.
Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
2 I skolen intet lägga dertill, som jag eder bjuder; och skolen ej heller taga der något ifrå; på det I mågen bevara Herrans edars Guds bud, som jag bjuder eder.
Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
3 Edor ögon hafva sett hvad Herren gjort hafver med BaalPeor; ty alla de som efterföljde BaalPeor, dem hafver Herren din Gud förgjort ibland eder.
Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
4 Men I som höllen eder intill Herran edar Gud, I lefven alle på denna dag.
Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
5 Si, jag hafver lärt eder bud och rätter, såsom Herren min Gud mig budit hafver, att I så göra skolen i landet, der I inkommande varden till att intaga det.
Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
6 Så behåller det nu, och görer det; ty så varder edor vishet och förstånd berömd för all folk, när de hörande varda all denna bud, så att de skola säga: Si, hvilket vist och förståndigt folk detta är, och ett härligit folk.
Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
7 Ty hvad folk är så härligit, hvilko gudarna så nalkas, såsom Herren vår Gud, så ofta som vi åkalle honom?
Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
8 Och hvar är något så härligit folk, som så rättfärdiga seder och bud hafver, såsom all denna lagen, som jag eder på denna dagen föregifver?
Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
9 Så förvara dig nu och dina själ granneliga, att du icke förgäter hvad för din ögon skedt är, och att det icke gånger utu dino hjerta i alla dina lifsdagar; och skall förkunna dinom barnom, och dinom barnabarnom,
Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
10 Den dagen, då du stod för Herranom dinom Gud vid berget Horeb, och Herren till mig sade: Församla mig folket, att jag skall låta dem höra min ord, och lära frukta mig i alla deras lifsdagar på jordene, och lära sin barn.
Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
11 Och I gingen fram, och stoden neder under berget, och berget brann halfväges upp till himmelen; och der var mörker, moln och töckna.
Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
12 Och Herren talade med eder midt utur elden; hans ords röst hörden I, men ingen liknelse sågen I, utan röstena.
Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
13 Och han förkunnade eder sitt förbund, det han eder böd att göra; nämliga de tio ord, och skref dem på två stentaflor.
Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
14 Och Herren böd mig på samma tiden, att jag skulle lära eder bud och rätter, att I derefter göra skullen uti de lande, der I indragen till att intaga det.
Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
15 Så förvarer nu edra själar väl; ty I hafven ingen liknelse sett på den dagen, då Herren talade med eder utur elden på bergena Horeb;
Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
16 På det I icke skolen förderfva eder och göra eder något beläte, det en man likt är eller qvinno;
kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
17 Eller djure på jordene, eller fogle under himmelen;
tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
18 Eller matke, som kräker på jordene, eller fiske i vattnena under jordene;
tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
19 Och att du icke heller upphäfver din ögon till himmelen, och ser solen, och månan, och stjernorna, hela himmelens här, och faller af, och tillbeder dem, och tjenar dem, hvilka Herren din Gud förskickat hafver allom folkom under hela himmelen.
Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
20 Men eder hafver Herren upptagit, och fört eder utu jernugnen, nämliga utur Egypten, att I skullen vara hans arffolk, som det ock är i denna dag.
Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
21 Och Herren vardt vred på mig för edra gerningars skull, så att han svor, att jag icke skulle komma öfver Jordanen, eller i det goda landet, som Herren din Gud dig till arfvedel gifva skall;
Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
22 Utan jag måste dö i detta land, och skall icke gå öfver Jordanen; men I skolen gå deröfver, och intaga det goda landet.
Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
23 Så tager eder nu vara, att I Herrans edars Guds förbund icke förgäten, det han med eder gjort hafver; och icke görer beläte till någrahanda liknelse, såsom Herren din Gud dig budit hafver.
Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
24 Förty Herren din Gud är en frätande eld, och en nitälskande Gud.
Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
25 När I nu föden barn, och barnabarn, och bon på landena, och förderfven eder, och gören eder beläte till någrahanda liknelse, så att I gören illa för Herranom edrom Gud, och förtörnen honom;
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
26 Så kallar jag i denna dag himmel och jord till vittne öfver eder, att I skolen snart förgås utaf landena, uti hvilket I ingån öfver Jordanen, till att intaga det. I skolen icke länge blifva deruti; utan skolen förgjorde varda;
Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
27 Och Herren skall förströ eder ibland folk, och I varden ett fögo folk qvart blifvande ibland Hedningarna, dit Herren eder drifvandes varder.
Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
28 Der skall du tjena afgudom, som menniskohandaverk äro, stock och sten, hvilke hvarken se eller höra, eller äta, eller lukta.
Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
29 Om du då der söker Herran din Gud, så skall du finna honom; om du söker honom af allo hjerta, och af allo själ.
Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
30 När du bedröfvad varder, och dig all denna tingen uppåkomma i de yttersta dagar, så skall du vända dig till Herran din Gud, och skall höra hans röst;
Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
31 Förty Herren din Gud är en barmhertig Gud; han varder dig icke öfvergifvandes, eller förderfvandes; och skall han icke förgäta det förbund med dina fäder, som han dem svorit hafver.
Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
32 Befråga efter förtiden, som för dig varit hafver, ifrå den dagen då Gud skop menniskona på jordene, ifrå den ena himmelens ända till den andra, om någon tid en sådana stor ting skedd, eller dess like någon tid hörd är;
Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
33 Att något folk hade hört Guds röst talandes utur elden, såsom du hört hafver, och likväl lefver?
Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
34 Eller om Gud försökt hafver att ingå, och taga sig ett folk midt utur eno folke, genom frestelse, genom tecken, genom under, genom strid, och genom mägtiga hand, och genom uträcktan arm, och genom stora syner, såsom Herren edar Gud allt detta med eder gjort hafver, för din ögon uti Egypten?
Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
35 Du hafver sett det, på det du skall veta, att Herren är allena Gud, och ingen annan.
A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
36 Af himmelen hafver han låtit dig höra sina röst, att han skulle lära dig; och på jordene hafver han låtit dig se sin stora eld, och utur elden hafver du hört hans ord;
Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
37 Derföre, att han dina fäder älskat, och deras säd efter dem utvalt hafver; och fört dig utur Egypten med sitt ansigte, genom sina stora magt;
torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
38 På det han skulle för dig fördrifva stor folk, och starkare än du äst, och föra dig derin, och gifva dig deras land till arfvedel, såsom det tillstår i denna dag.
Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
39 Så skall du nu veta i dag, och lägga det på hjertat, att Herren är en Gud, ofvan i himmelen, och nedre uppå jordene, och ingen annan;
Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
40 Att du håller hans rätter och bud, som jag i dag bjuder dig, så varder dig och dinom barnom efter dig väl gåendes, att ditt lif skall länge vara i landena, som Herren din Gud dig gifver evärdeliga.
Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
41 Då afskiljde Mose tre städer hinsidon Jordan, österut;
Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
42 Att dit fly skulle ho som sin nästa ihjälsloge med våda, och tillförene icke hade varit hans ovän; den skulle fly in uti en af de städer, på det han måtte blifva vid lif;
Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
43 Bezer i öknene på den slättmarkene ibland de Rubeniter, och Ramoth i Gilead ibland de Gaditer, och Golan i Basan ibland de Manassiter.
Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
44 Detta är den lag, som Mose Israels barnom föregaf;
Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
45 Och detta är vittnesbördet, och bud, och rätter, som Mose sade Israels barnom, då de utur Egypten dragne voro;
Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
46 Hinsidon Jordan uti den dalenom in mot Peors hus, uti Sihons lande, de Amoreers Konungs, som i Hesbon bodde, hvilken Mose och Israels barn slogo, då de utur Egypten komne voro,
Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
47 Och togo hans land in; dertill Ogs land, Konungens i Basan, de två Amoreers Konungars, som på hinsidon Jordan voro, österut;
Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
48 Ifrån Aroer, hvilken på den bäckens strand vid Arnon ligger, intill berget Sion, det är Hermon;
Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
49 Och allt släta landet hinsidon Jordan, österut, allt intill hafvet, på slättene, nedanför berget Pisga.
Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.

< 5 Mosebok 4 >