< 5 Mosebok 3 >

1 Och vi vände om, och drogo upp, den vägen till Basan. Och Og, Konungen i Basan, drog ut emot oss med allt sitt folk, till att strida vid Edrei.
Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
2 Men Herren sade till mig: Frukta dig intet för honom; ty jag hafver gifvit honom i dina händer, och allt hans folk med hans land, och du skall göra med honom, såsom du gjorde med Sihon, de Amoreers Konung, den i Hesbon satt.
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
3 Alltså gaf Herren vår Gud ock Konung Og i Basan i våra händer, med allt hans folk, så att vi sloge honom, tilldess honom intet igenblef.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
4 På samma tid vunne vi alla hans städer, och var ingen stad den vi honom icke aftogom; sextio städer, hela den ängden Argob i Ogs rike, som var i Basan;
Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
5 Alle desse städer voro faste med höga murar, portar och bommar, förutan andra ganska många små städer, som ingen mur hade;
Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
6 Och gåfvom dem tillspillo, såsom vi, med Sihon, Konungenom i Hesbon, gjort hade; alla städer gåfve vi tillspillo, både med män, qvinnor och barn.
Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
7 Men allan boskapen, och rofvet af städerna toge vi för oss.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
8 Alltså toge vi i den tiden landet utu de två Amoreers Konungars händer på hinsidon Jordan, ifrå den bäcken vid Arnon, allt intill det berget Hermon;
Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
9 Hvilket de Sidonier Sirion kalla; men de Amoreer kalla det Senir;
(Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
10 Alla de städer på slättene, och hela Gilead, och hela Basan, allt intill Salcha och Edrei, som äro städer i Ogs rike i Basan.
Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
11 Ty allena Konung Og i Basan var ännu igen utaf de Resar. Si, hans säng af jern är här i Rabbath, som hörer Ammons barnom till, nio alnar lång, och fyra alnar bred, efter ens mans armbåga.
(Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
12 Så toge vi då landet in på den tiden, ifrån Aroer, som ligger när bäcken vid Arnon; och halfva landet af Gileads berg, med dess städer, gaf jag de Rubeniter och Gaditer.
Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
13 Men det öfver var i Gilead, och hela Basan af Ogs rike, gaf jag den halfva slägtene Manasse; den hela ängden Argob med hela Basan, som kallas de Resars land.
Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
14 Jair, Manasse son, fick den hela ängden Argob, allt intill Gessuri och Maachathi landsändar; och kallade Basan efter sitt namn, HavothJair, allt intill denna dag.
Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
15 Men Machir gaf jag Gilead.
Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
16 Och de Rubeniter och Gaditer gaf jag en del af Gilead, allt intill bäcken vid Arnon, midt i bäcken, der landamäret är, och allt intill den bäcken Jabbok, der landamäret är för Ammons barn;
ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
17 Dertill den slättmarkena, och Jordan, den landamäret är, ifrå Cinnereth intill hafvet vid slättmarkena; nämliga salthafvet nedan vid berget Pisga österut.
Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
18 Och jag böd eder på samma tiden, och sade: Herren edar Gud hafver gifvit eder detta landet att intaga det; så drager nu väpnade för edra bröder Israels barn, alle I som stridsamme ären;
Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
19 Förutan edra hustrur, barn och boskap; ty jag vet, att I hafven mycken boskap; låter dem blifva uti edra städer, som jag eder gifvit hafver;
Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
20 Tilldess Herren låter ock edra bröder komma till rolighet såsom eder, att de ock intaga det land, som Herren deras Gud dem gifva skall på hinsidon Jordan; sedan skolen I omvända till edor besittning, den jag eder gifvit hafver.
títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
21 Och jag böd Josua på samma tiden, och sade: Din ögon hafva sett allt det som Herren edar Gud dessa två Konungar gjort hafver; så varder Herren ock görandes all Konungarike, dit du drager.
Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
22 Frukter eder intet för dem; ty Herren edar Gud strider för eder.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
23 Och jag bad Herran på den tiden, och sade:
Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
24 Herre, Herre, du hafver begynt visa dinom tjenare dina härlighet och dina starka hand; ty hvilken är den Gud i himmelen eller på jordene, som förmår efter din verk och din magt göra?
“Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
25 Låt mig gå och se det goda landet, på hinsidon Jordan; de goda berg, och Libanon.
Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
26 Men Herren vardt vred på mig för edra skull, och bönhörde mig intet; utan Herren sade till mig: Låt blifvat: tala intet mer derom för mig.
Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
27 Stig upp på höjden af berget Pisga, och häf din ögon upp vesterut, och norrut, och söderut, och österut, och se det med ögonen; ty du skall intet gå utöfver denna Jordan;
Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
28 Utan bjud Josua, att han är tröst och frimodig; förty han skall gå öfver Jordan för folket, och skall utskifta dem landet, som du seendes varder.
Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
29 Så blefvo vi då i den dalen in mot Peors hus.
Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.

< 5 Mosebok 3 >