< 2 Kungaboken 10 >

1 Och Achab hade sjutio söner i Samarien; och Jehu skref bref, och sände till Samarien till de öfversta i Israels stad, till de äldsta, och Achabs förmyndare, hvilket så lydde:
Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
2 När detta bref kommer till eder, när hvilkom edars herras söner äro, hans vagnar, hästar, faste städer och rustning;
“Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
3 Så ser till, hvilken bäst och likast är ibland edars herras söner, och sätter honom på hans faders stol, och strider för edars herras hus.
yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
4 Men de fruktade sig ganska fast, och sade: Si, två Konungar hafva icke blifvit ståndande för honom; huru skulle vi då stå?
Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
5 Och de som voro öfver huset, och öfver staden, och de äldste, och förmyndarena, sände bort till Jehu, och läto säga honom: Vi äre dine tjenare, vi vilje göra allt det du säger oss; vi vilje ingen göra till Konung; gör hvad dig täckes.
Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
6 Då skref han ett annat bref till dem; det lydde alltså: Ären I mine, och lyden mine röst, så tager hufvuden af de män edars herras söner, och förer dem i morgon bittida till mig i Jisreel. Och Konungssönerna voro sjutio män, och de ypperste i staden uppfödde dem.
Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
7 Då nu brefvet kom till dem, togo de Konungssönerna, och dråpo sjutio män, och lade deras hufvud i korgar, och sände dem till honom i Jisreel.
Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
8 Och då bådet kom, och bådade honom det, och sade: De hafva fört hit Konungssönernas hufvud; sade han: Lägger dem i två hopar för stadsporten, intill morgons.
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
9 Och om morgonen, när han utgick, trädde han dit, och sade till allt folket: Ären I rättvise? Si, hafver jag gjort ett förbund emot min herra, och dräpit honom; ho hafver då slagit alla dessa?
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
10 Så må I ju se, att intet Herrans ord är på jordena fallet, som Herren talat hafver emot Achabs hus; och Herren hafver gjort såsom han talat hafver genom sin tjenare Elia.
Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
11 Alltså slog Jehu alla dem som qvare voro af Achabs hus i Jisreel, alla hans yppersta, hans vänner, och hans Prester, tilldess icke en var qvar;
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
12 Och stod upp, och drog bort till Samarien. Men i vägen var ett herdahus.
Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
13 Der råkade Jehu vid Ahasia, Juda Konungs, bröder, och sade: Ho ären I? De sade: Vi äre Ahasia bröder, och drage ned till att helsa Konungens barn, och Drottningenes barn.
Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
14 Han sade: Griper dem lefvande. Och de grepo dem lefvande, och dråpo dem vid brunnen när herdahuset, två och fyratio män; och lät icke en af dem slippa.
“Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
15 Och då han drog dädan, fann han Jonadab, Rechabs son, den honom mötte, och helsade honom, och sade till honom: Är ditt hjerta rätt, såsom mitt hjerta med dino hjerta? Jonadab sade: Ja. Är det så, sade han, så räck mig dina hand. Och han räckte honom sina hand; och han lät honom sitta uppe när sig på vagnen;
Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
16 Och sade: Kom med mig, och se mitt nit om Herran. Och de förde honom med honom på hans vagn.
Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
17 Då han kom till Samarien, slog han allt det som qvart var af Achab i Samarien, tilldess han förgjorde honom, efter Herrans ord, som han till Elia talat hade.
Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
18 Och Jehu församlade allt folket, och lät säga till dem: Achab hafver fögo tjent Baal; Jehu vill bättre tjena honom.
Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
19 Så låt nu kalla alla Baals Propheter, alla hans tjenare, och alla hans Prester, till mig, så att ingen är borto; förty jag hafver ett stort offer till att göra Baal; hvilken borto är, den skall icke lefva. Men Jehu gjorde detta med listighet, att han måtte förgöra Baals tjenare.
Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
20 Och Jehu sade: Helger Baal ena högtid, och låter den utropa.
Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
21 Och sände Jehu i hela Israel, och lät komma alla Baals tjenare, så att ingen qvar var, som icke kom. Och de kommo i Baals hus; så att Baals hus vardt fullt i all rum.
Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
22 Då sade han till dem, som voro öfver klädehuset: Bärer ut kläder för alla Baals tjenare. Och de båro kläder ut.
Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
23 Och Jehu gick in uti Baals hus med Jonadab, Rechabs son, och sade till Baals tjenare: Ransaker, och ser till, att ingen Herrans tjenare är ibland eder, utan Baals tjenare allena.
Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
24 Och som de kommo in till att göra offer och bränneoffer, beställde Jehu sig åttatio män utanföre, och sade: Ho som släpper någon af männerna, som jag får under edra händer, hans själ skall vara för hans själ.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
25 När nu bränneoffret fullkomnadt var, sade Jehu till drabanterna och höfvitsmännerna: Går in, och slår dem allasamman; låter ingen komma derut. Och de slogo dem med svärdsegg, och drabanterna och höfvitsmännerna hofvo dem bort. Och de gingo till Baals hus stad;
Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
26 Och togo ut de stodar i Baals hus, och brände dem upp;
Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
27 Och slogo sönder Baals stodar, samt med Baals hus; och gjorde der ett hemligt hus af, allt intill denna dag.
Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
28 Alltså förgjorde Jehu Baal utur Israel.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
29 Men ifrå Jerobeams, Nebats sons, synder, den Israel kom till att synda, gick Jehu icke, och öfvergaf icke de guldkalfvar i BethEl och i Dan.
Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
30 Och Herren sade till Jehu: Derföre, att du hafver viljog varit till att göra min vilja, och hafver gjort på Achabs hus allt det i mino hjerta var, skola dina söner sitta dig på Israel stol intill fjerde led.
Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
31 Dock höll icke Jehu, att han i Herrans Israels Guds lag vandrade af allo hjerta; ty han trädde icke ifrå Jerobeams synder, som kom Israel till att synda.
Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
32 På den tiden begynte Herren ledas vid Israel; ty Hasael slog dem i alla Israels gränsor;
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
33 Ifrå Jordan österut, och hela Gilead, de Gaditers, Rubeniters, och Manassiters land, ifrån Aroer, som ligger när den bäcken vid Arnon; och Gilead, och Basan.
Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
34 Hvad nu mer af Jehu sägande är, och allt det han gjort hafver, och all hans magt, si, det är skrifvet uti Israels Konungars Chrönico.
Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
35 Och Jehu afsomnade med sina fäder; och de begrofvo honom i Samarien; och Joahas hans son vardt Konung i hans stad.
Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
36 Men tiden, som Jehu öfver Israel regerade i Samarien, är åtta och tjugu år.
Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.

< 2 Kungaboken 10 >