< 1 Samuelsboken 22 >
1 David gick dädan, och flydde bort uti den kulon Adullam. Då hans bröder det hörde, och hela hans faders hus, kommo de ditned till honom.
Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
2 Och till honom församlade sig allehanda män, som i nöd, i gäld och bedröfvadt hjerta voro, och han vardt deras höfvitsman, så att när honom voro vid fyrahundrade män.
Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
3 Och David gick dädan till Mizpa uti de Moabiters land, och sade till de Moabiters Konung: Låt min fader och min moder gå ut och in med eder, tilldess jag får se hvad Gud vill göra med mig.
Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
4 Och han lät dem in för de Moabiters Konung, att de voro när honom så länge som David var på borgene.
Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
5 Men den Propheten Gad sade till David: Blif icke på borgene, utan gack bort i Juda land. Så gick David åstad, och kom uti den skogen Hareth.
Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
6 Och det kom för Saul, att David och de män, som när honom voro, voro sedde. Som nu Saul bodde i Gibea i en lund i Rama, hade han sitt spjut i handene, och alla hans tjenare stodo bredevid honom.
Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
7 Då sade Saul till sina tjenare, som stodo bredevid honom: Hörer, I Jemini barn, månn ock Isai son skola gifva eder allom åkrar och vingårdar, och göra eder alla till öfverstar öfver tusende, och öfver hundrade;
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
8 Att I alle hafven förbundit eder emot mig, och ingen är, som det för min öron uppenbarar, efter min son hafver ock gjort ett förbund med Isai son? Är ingen ibland eder, hvilkom det gör ondt för mina skull, och uppenbarar det för min öron? Ty min son hafver uppväckt min tjenare emot mig; att han skall gå mig efter, såsom för ögon är.
Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
9 Så svarade Doeg den Edomeen, som stod ibland Sauls tjenare, och sade: Jag såg Isai son, att han kom till Nobe till Ahimelech, Ahitobs son.
Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
10 Han frågade om honom Herran, och gaf honom spisning och Goliaths den Philisteens svärd.
Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
11 Då sände Konungen åstad, och lät kalla Presten Ahimelech, Ahitobs son, och hela hans faders hus, Presterna som voro i Nobe; och de kommo alle till Konungen.
Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
12 Och Saul sade: Hör du, Ahitobs son. Han sade: Här är jag, min herre.
Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
13 Och Saul sade till honom: Hvi hafven I gjort ett förbund emot mig, du och Isai son, så att du hafver gifvit honom bröd och svärd, och frågat Gud för honom, på det du skulle uppväcka honom, till att han skulle gå mig efter, såsom för ögon är?
Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
14 Ahimelech svarade Konungenom, och sade: Och ho är ibland alla dina tjenare sådana som David, trogen och Konungens måg, och går i dine lydno, och är mycket afhållen i ditt hus?
Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
15 Hafver jag nu först i dag begynt fråga Gud för honom? Det vare långt ifrå mig; Konungen lägge sin tjenare icke sådant till i allo mins faders huse; förty din tjenare hafver intet vetat af allt detta, hvarken litet eller stort.
Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
16 Men Konungen sade: Ahimelech, du måste döden dö, du och hela dins faders hus.
Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
17 Och Konungen sade till sina drabanter, som när honom stodo: Vänder eder, och dräper Herrans Prester; förty deras hand är ock med David; och då de visste att han flydde, underviste de mig det icke. Men Konungens tjenare ville icke komma deras händer vid Herrans Prester, och slå dem.
Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
18 Då sade Konungen till Doeg: Vänd du dig, och slå Presterna. Doeg den Edomeen vände sig, och slog Presterna, så att den dagen blefvo döde fem och åttatio män, som drogo linnan lifkjortel.
Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
19 Och Presternas stad Nobe slog han med svärdsegg, både män och qvinnor, barn och dem som didde, fä och åsnar, och får.
Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
20 Men en Ahimelechs son, Ahitobs sons, benämnd AbJathar, slapp undan, och flydde bort till David;
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
21 Och sade honom, att Saul hade dräpit Herrans Prester.
Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
22 Men David sade till AbJathar: Jag visste väl den dagen, då den Edomeen Doeg der var, att han skulle säga det Saul. Jag är skyldig för alla dins faders hus själar.
Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
23 Blif när mig, och frukta dig intet. Den som står efter mitt lif, han skall ock stå efter ditt lif, och du skall med mig blifva förvarad.
Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”