< 1 Samuelsboken 12 >

1 Då sade Samuel till hela Israel: Si, jag hafver hört edra röst uti allt det I mig sagt hafven, och hafver gjort en Konung öfver eder.
Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
2 Och si, der går nu edar Konung för eder; men jag är gammal och grå vorden, och mine söner äro när eder, och jag hafver gångit för eder, ifrå min ungdom allt intill denna dag.
Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
3 Si, här är jag: Svarer mig inför Herranom och hans smorda, om jag någons mans oxa eller åsna tagit hafver? Om jag hafver någrom gjort öfvervåld och orätt? Om jag någon undertryckt hafver? Om jag af någons mans hand hafver tagit gåfvor, och hållit det hemliga? Så vill jag gifva eder det igen.
Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
4 De sade: Du hafver intet öfvervåld eller orätt gjort oss, ej heller någon undertryckt; ej heller af någons mans hand något tagit.
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
5 Han sade till dem: Herren och hans smorde vare vittne emot eder i dag, att i intet hafven funnit i mine hand. De sade: Ja, vare vittne.
Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
6 Och Samuel sade till folket: Ja, Herren, som Mose och Aaron gjort hafver, och förde edra fäder utur Egypti land.
Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
7 Så går nu fram, att jag må döma eder för Herranom, öfver all Herrans rättfärdighet, som han med eder och edra fäder gjort hafver.
Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
8 Då Jacob var kommen in uti Egypten, ropade edra fäder till Herran. Och Herren sände Mose och Aaron, att de skulle föra edra fäder utur Egypten, och lät bo dem på detta rum.
“Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
9 Men när de förgåto Herran sin Gud, sålde han dem under Sisera våld, höfvitsmansens i Hazor, och uti de Philisteers våld, och uti de Moabiters Konungs våld; de stridde emot dem.
“Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
10 Och de ropade till Herran, och sade: Vi hafve syndat, att vi hafve öfvergifvit Herran, och tjent Baalim och Astaroth; men frälsa oss nu ifrå våra fiendars hand, så vilje vi tjena dig.
Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
11 Då sände Herren JerubBaal, Bedan, Jephthah och Samuel, och frälste eder utur edra fiendars händer, allt omkring, och lät eder bo tryggeliga.
Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
12 När I då sågen att Nahas, Ammons barnas Konung, Kom emot eder, saden I till mig: Icke du, utan en Konung skall råda öfver oss; ändock Herren edar Gud var edar Konung.
“Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
13 Nu, här hafven I edar Konung, den I utvalt och begärat hafven; ty, si, Herren hafver satt en Konung öfver eder.
Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
14 Om I nu frukten Herran, och tjenen honom, och hören hans röst, och icke ären Herrans mun ohörige, så skolen både I och edar Konung, som öfver eder råder, efterfölja Herran edar Gud.
Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
15 Om I icke hören Herrans röst, utan ären Herrans mun ohörige, så skall Herrans hand vara emot eder och edra fäder.
ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
16 Går också nu fram, och ser det stora ärende, som Herren göra skall för edor ögon.
“Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
17 Är icke nu hveteanden? Dock vill jag åkalla Herran, att han skall låta dundra och regna, att I skolen förnimma och se det stora onda, som I för Herrans ögon gjort hafven, att I hafven bedts eder Konung.
Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
18 Och då Samuel åkallade Herran, lät Herren den samma dagen dundra och regna; då fruktade allt folket Herran och Samuel ganska storliga;
Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
19 Och sade alle till Samuel: Bed för dina tjenare Herran din Gud, att vi icke dö; ty öfver alla våra synder hafve vi ock gjort detta onda, att vi beddes oss Konung.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
20 Och Samuel sade till folket: Frukter eder intet, I hafven sannerliga gjort allt det onda; dock träder icke af ifrå Herranom, utan tjener Herranom af allo hjerta.
Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
21 Och viker icke efter fåfängelig ting; ty det gagnar eder intet, och kan intet hjelpa eder, efter det en fåfängelig ting är.
Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
22 Förty Herren öfvergifver icke sitt folk, för sitt stora Namns skull; ty Herren hafver begynt till att göra eder sig sjelfvom till ett folk.
Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
23 Vare ock fjerran ifrå mig, att jag så skulle synda emot Herran, att jag skulle aflåta bedja för eder, och lära eder den goda och rätta vägen.
Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
24 Allenast frukter Herran, och tjener honom troliga af allo hjerta; förty I hafven sett huru stor ting han gör med eder.
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
25 Men om I gören det ondt är, så skolen både I och edar Konung förgås.
Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”

< 1 Samuelsboken 12 >