< Sofonías 2 >

1 Reúnase, reúnanse todos, oh nación indeseable;
Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
2 Antes de que el decreto del Señor entre en vigencia; antes de que el Señor te envíe violentamente en fuga como la basura de grano; antes de que la ira ardiente del Señor venga sobre ti, antes que el día de la ira del Señor venga sobre ti.
kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà, kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín, kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
3 Busquen al Señor, todos los humildes en la tierra, que han hecho lo que es correcto a sus ojos; busca la justicia y un corazón tranquilo; puede ser que estés protegido en el día de la ira del Señor.
Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà, ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ. Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú, bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
4 Porque Gaza será abandonada y Ascalón se convertirá en basura; expulsarán a Asdod a mitad del día, y los de Ecrón serán desarraigados.
Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀, Aṣkeloni yóò sì dahoro. Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde, a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
5 ¡Ay! de la gente que vive junto al mar, la nación de Creta! La palabra del Señor está contra ti, oh Canaán, la tierra de los filisteos; Enviaré destrucción sobre ti hasta que no haya nadie viviendo en ti.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun, ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti; ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani, ilẹ̀ àwọn ara Filistini. “Èmi yóò pa yín run, ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
6 Y la tierra junto al mar será tierra de pasto, con casas para los cuidadores de ovejas y lugares amurallados para los rebaños.
Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti, ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
7 La tierra junto al mar será para el remanente de los hijos de Judá; junto al mar darán comida a sus rebaños; en las casas de Ascalón reposarán por la tarde; porque el Señor su Dios los visitará y los hará volver de su cautiverio.
Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda, níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran. Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́. Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò, yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
8 Mis oídos han escuchado los insultos de Moab y las injurias de los hijos de Amón, que han dicho contra mi pueblo, se han engrandecido contra el límite de su tierra.
“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni, àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
9 Por esta causa, según mi vida, dice el Señor de los ejércitos, el Dios de Israel, Moab se convertirá verdaderamente como Sodoma y los hijos de Amón como Gomorra, campo de espinos y minas de sal y desolación para siempre; el remanente de mi gente tomará sus propiedades, el remanente de mi nación tomará su herencia.
Nítorí náà, bí Èmi tí wà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí, “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu, àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra, ibi tí ó kún fún yèrèpè, àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé. Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn; àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
10 Este será su destino debido a su orgullo, porque han dicho mal, alzándose contra el pueblo del Señor de los ejércitos.
Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn, nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 El Señor será terrible contra ellos, porque hará que todos los dioses de la tierra sean débiles; y los hombres descenderán delante de él en adoración, todos desde su lugar, incluso todas las islas.
Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn; nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run. Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn, olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
12 Y ustedes, etíopes, serán muertos por mi espada.
“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú, a ó fi idà mi pa yín.”
13 Y su mano se extenderá contra el norte, para la destrucción de Asiria; y hará que Nínive sea una desolación y se seque como el desierto.
Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá, yóò sì pa Asiria run, yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.
14 Y los rebaños reposarán en medio de ella, todas las bestias del Valle; el pelícano y el puercoespín se instalarán en la parte superior de sus pilares; la lechuza llorará en la ventana; el cuervo se verá en la puerta.
Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀, àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè. Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀. Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé, ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà, òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
15 Este es el pueblo que estaba lleno de alegría, viviendo sin temor al peligro, diciendo en su corazón: Yo soy, y no hay otro más que yo; cómo ha sido destruido, se ha convertido en un lugar para que las bestias descansen! Todo él que pase junto a ella silbará y meneará su mano.
Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu. Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé, “Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.” Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́, ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó! Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀ yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.

< Sofonías 2 >