< Salmos 124 >
1 Si no hubiera sido el Señor quien estuvo de nuestro lado (que Israel ahora diga);
Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
2 Si no hubiera sido el Señor quien estuvo de nuestro lado, cuando los hombres vinieron contra nosotros;
ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
3 Habrían hecho una comida de nosotros mientras vivíamos, en el calor de su ira contra nosotros:
nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
4 Hubiéramos estado cubiertos por las aguas; las corrientes habrían recorrido nuestra alma;
nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
5 Sí, las aguas del orgullo habrían pasado por nuestra alma.
nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
6 Alabado sea el Señor, que no nos ha dejado herir con sus dientes.
Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
7 Nuestra alma se ha liberado como un pájaro de la red de los cazadores; la red está rota, y somos libres.
Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
8 Nuestra ayuda está en el nombre del Señor, el hacedor del cielo y de la tierra.
Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.