< Salmos 120 >
1 En mi angustia, mi llanto subió al Señor, y él me dio una respuesta.
Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
2 Oh Señor, sé el salvador de mi alma de los labios mentirosos y de la lengua del engaño.
Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
3 ¿Qué castigo te dará? ¿Qué más te hará él, lengua falsa?
Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
4 Flechas afiladas del fuerte y fuego ardiente.
Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
5 La aflicción es mía porque soy extraño en Mesec, y vivo en las tiendas de Cedar.
Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
6 Mi alma ha estado viviendo por mucho tiempo con los que odian la paz.
Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
7 Estoy a favor de la paz; pero cuando digo eso, están a favor de la guerra.
Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.