< Salmos 105 >
1 ¡Alabado sea el Señor! den honor a su nombre, hablando de sus obras entre los pueblos.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Deje que su voz suene en canciones y melodía; deja que todos tus pensamientos sean de la maravilla de sus obras.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Ten la gloria en su santo nombre; que los corazones de aquellos que están buscando al Señor estén contentos.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Que tu búsqueda sea para el Señor y para su fortaleza; deja que tus corazones vuelvan a él.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Recuerden las grandes obras que ha hecho; sus maravillas y las decisiones de su boca;
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Oh descendencia de Abraham, su siervo, hijos de Jacob, sus amados.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Él es el Señor nuestro Dios; él es el juez de toda la tierra.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Ha guardado para siempre su pacto, la palabra que dio por mil generaciones;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 El acuerdo que hizo con Abraham, y su juramento a Isaac;
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Y la dio a Jacob por ley, y a Israel por eterno acuerdo;
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Diciendo: A ti daré la tierra de Canaán, como herencia que te toca.
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Cuando todavía eran pequeños en número, y extraños en la tierra;
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Cuando anduvieron de una nación a otra, y de un reino a otro pueblo.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Él no dejaría que nadie los hiciera mal; incluso advirtió a reyes,
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 Diciendo: No pongas tu mano sobre los que han sido marcados con mi aceite santo, y no hagan mal a mis profetas.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Y quitó toda la comida de la tierra, y la gente quedó sin pan.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Envió un hombre delante de ellos, a José, que fue dado como siervo por un precio:
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Sus pies estaban fijos en cadenas; su cuello fue puesto en la cárcel;
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Hasta el momento en que su palabra se hizo realidad; fue probado por la palabra del Señor.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 El rey envió hombres a quitar sus cadenas; el gobernante de la gente, que lo dejó en libertad.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Lo hizo señor de su casa y gobernador de todo lo que tenía;
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 Para dar a sus jefes que enseñanza a su placer, y para que sus legisladores puedan obtener la sabiduría de él.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Entonces Israel vino a Egipto, y Jacob estaba viviendo en la tierra de Cam.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Y su pueblo se engrandeció grandemente, y se hizo más fuerte que los que estaban contra ellos.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Sus corazones se volvieron para odiar a su pueblo, por lo que hicieron designios secretos contra ellos.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Envió a Moisés, su siervo, y Aarón, el hombre de su elección.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Hizo ver sus señales entre el pueblo y sus maravillas en la tierra de Cam.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Envió noche negra y oscureció; y ellos no fueron en contra de su palabra.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Según su palabra, sus aguas se convirtieron en sangre, y él envió la muerte sobre todos sus peces.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Su tierra estaba llena de ranas, incluso en las habitaciones del rey.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 El dio la palabra, y vino la mosca del perro, y los insectos sobre toda la tierra.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Les dio hielo para la lluvia y fuego ardiente en su tierra.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Y destruyó sus viñas y sus higueras, y destruyeron los árboles de su tierra.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Por su palabra vinieron langostas, y langostas jóvenes más de las que pueden ser contadas,
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 Y pusieron fin a todas las plantas de su tierra, y se comieron todos los frutos de la tierra.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Él mató al primer hijo de cada familia en la tierra, los primeros frutos de su fuerza.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Sacó a su pueblo con plata y oro; no había entre ellos persona débil.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Egipto se alegró cuando se fueron; porque el temor de ellos había caído sobre ellos.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Una nube se extendía sobre ellos para cubrirse; y él envió fuego para dar luz en la noche.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 A petición del pueblo, envió pájaros y les dio el pan del cielo como alimento.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Su mano hizo abrir la roca, y las aguas brotaron; descendieron por los lugares secos como un río.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Porque él tuvo presente su santa palabra, y Abraham, su siervo.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Y se llevó a su pueblo con alegría, los hombres de su selección con alegres gritos:
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 Y les dio las tierras de las naciones; y tomaron el trabajo de los pueblos por herencia;
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 Para que guarden sus órdenes, y sean fieles a sus leyes. Alaba al Señor.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.