< Proverbios 24 >
1 No tengan envidia de los hombres malvados, ni ningún deseo de estar con ellos:
Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
2 porque el propósito de sus corazones es la destrucción, y sus labios están hablando de causar problemas.
nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
3 La construcción de una casa es por sabiduría, y por la razón se fortalece:
Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
4 Y por el conocimiento, sus habitaciones están llenas de todas las cosas queridas y agradables.
nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
5 El sabio es fuerte; y un hombre de conocimiento aumenta la fortaleza.
Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
6 Porque guiándote sabiamente, vencerás en la guerra; y en varios guías sabios está la victoria.
Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
7 La sabiduría está fuera del poder del insensato: mantiene su boca cerrada en el lugar público.
Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
8 Aquel cuyo propósito es malo será nombrado hombre de malos designios.
Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
9 El propósito del necio es el pecado; y el que odia a la autoridad es repugnante para los demás.
Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
10 Si cedes en el día de la angustia, tu fuerza es pequeña.
Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
11 Sé el salvador de los que son entregados a la muerte, y no retires la ayuda de aquellos que están cayendo en la destrucción.
Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
12 Si dices: Mira, no teníamos conocimiento de esto: ¿no lo piensa el probador de corazones? y el que guarda tu alma, ¿no lo sabe? ¿Y no dará a cada hombre la recompensa de su trabajo?
Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
13 Hijo mío, toma miel, porque es bueno; y la miel que fluye, que es dulce a tu gusto:
Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
14 Así que deja que tu deseo sea sabiduría: si la tienes, habrá un futuro, y tu esperanza no será cortada.
Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
15 No hagas planes malvados, oh malhechor, contra los campos del hombre recto, o envíes destrucción sobre su lugar de reposo:
Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
16 Porque un hombre recto, después de haber caído siete veces, se levantará otra vez; pero los malos caerán en él mal.
nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
17 No te alegres por la caída de tu adversario, y no se alegre tu corazón por su caída:
Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
18 Por temor de que el Señor lo vea, y pueda ser malo a sus ojos, y su ira se aleje de él.
Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
19 No te preocupes por los malvados, ni tengas envidia de los pecadores:
Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
20 Porque no habrá futuro para el malvado; la luz de los pecadores será apagada.
nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
21 Hijo mío, teme al Señor y al rey; no tengas nada que ver con los inestables:
Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
22 porque su caída vendrá repentinamente; y ¿quién tiene conocimiento de la ruina que viene de ambos?
Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
23 Estos son más dichos de los sabios: Tener preferencia por la posición de una persona cuando se juzga no es bueno.
Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
24 El que dice al malvado, eres recto, será maldecido por los pueblos y aborrecido por las naciones.
Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
25 Pero aquellos que le castigan les irá bien, y una bendición de bien vendrá sobre ellos.
Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
26 Él es como si diera un beso con sus labios cuando da una respuesta correcta.
Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
27 Pon en orden tu trabajo afuera, y prepáralo en el campo; y después de eso, ve a la construcción de tu casa.
Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
28 No seas un testigo falso contra tu prójimo, o deja que tus labios digan falso testimonio.
Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
29 No digas: haré con él lo que me ha hecho; Le daré al hombre la recompensa de su trabajo.
Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
30 Fui por el campo del que odia el trabajo y por la viña del hombre sin sentido;
Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
31 Y todo estaba lleno de espinas, y cubierto de plantas deshechas, y su muro de piedra se quebró.
ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
32 Luego mirándolo, pensé: lo vi, y obtuve enseñanza de él.
Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
33 Un poco de sueño, un poco de descanso, un poco de doblar las manos en el sueño:
oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
34 Entonces la pérdida caerá sobre ti como un forajido, y tu necesidad como un hombre armado.
òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.