< Números 34 >
1 Y él Señor dijo a Moisés:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Da órdenes a los hijos de Israel y diles: Cuando entres en la tierra de Canaán; (esta es la tierra que debe ser tu herencia, la tierra de Canaán dentro de estos límites).
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
3 Entonces él límite del lado sur será el desierto de Zin al lado de Edom, y tu límite en el sur será del extremo este del Mar salado.
“‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
4 Y redondea al sur de la pendiente de Acrabim, y luego a Zin: y su dirección será al sur de Cades-barnea, y llegará hasta Hasar-adar y luego a Azmon.
kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
5 Y desde Azmon irá hasta la corriente de Egipto hasta el mar.
Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
6 Y para tu límite en el oeste tendrás el Gran Mar y su borde, este será tu límite en el oeste.
Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
7 Y tu límite en el norte será la línea desde el Gran Mar hasta el Monte Hor:
Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
8 Y desde el monte Hor la línea irá en dirección a Hamat; el punto más lejano será en Zedad:
àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
9 Y el límite continuará hasta Zifrón, con su punto más lejano en Hazar-enán: este será tu límite en el norte.
tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
10 Y en el este, tu límite se marcará desde Hazar-enán hasta Sefam,
Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
11 Bajando de Sefam a Ribla en el lado este de Ain, y hasta el lado este del mar de Cineret:
Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
12 Y así hasta el Jordán, extendiéndose hasta el Mar Salado; toda la tierra dentro de estos límites será tuya.
Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
13 Entonces Moisés dio órdenes a los hijos de Israel, diciendo: Esta es la tierra que debe ser tu herencia, por la decisión del Señor, que por orden del Señor se debe dar a las nueve tribus y la media tribu;
Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
14 A la tribu de los hijos de Rubén, por las familias de sus padres, y a la tribu de los hijos de Gad, por las familias de sus padres, y a la media tribu de Manasés, se les ha dado su patrimonio.
Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
15 A las dos tribus y la media tribu se les ha dado su herencia en el otro lado del Jordán en Jericó, en el este mirando hacia el amanecer.
Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
16 Y él Señor dijo a Moisés:
Olúwa sọ fún Mose pé,
17 Estos son los nombres de los hombres que repartirán la tierra entre ustedes: el sacerdote Eleazar y Josué, el hijo de Nun.
“Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
18 Y debes tomar un jefe de cada tribu para hacer la distribución de la tierra.
Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19 Y estos son los nombres de los hombres: de la tribu de Judá, Caleb, hijo de Jefone.
“Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
20 Y de la tribu de los hijos de Simeón, Semuel, hijo de Amiud.
Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
21 De la tribu de Benjamín, Elidad, el hijo de Quislon.
Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
22 Y de la tribu de los hijos de Dan, un jefe, Buqui, el hijo de Jogli.
Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
23 De los hijos de José: de la tribu de los hijos de Manasés, un jefe, Haniel, el hijo de Efod.
Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
24 Y de la tribu de los hijos de Efraín, un jefe, Kemuel, hijo de Siftan.
Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
25 Y de la tribu de los hijos de Zabulón, un jefe, Elizafán, hijo de Parnac.
Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
26 Y de la tribu de los hijos de Isacar, un jefe, Paltiel, el hijo de Azán.
Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
27 Y de la tribu de los hijos de Aser, un jefe, Ahiud, el hijo de Selomi.
Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
28 Y de la tribu de los hijos de Neftalí, un jefe, Pedael, el hijo de Amiud.
Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
29 Estos son aquellos a quienes el Señor dio órdenes de hacer la distribución de la herencia entre los hijos de Israel en la tierra de Canaán.
Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.