< Nehemías 12 >

1 Estos son los sacerdotes y los levitas que subieron con Zorobabel, el hijo de Salatiel, y Josué: Seraías, Jeremías, Esdras,
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
2 Amarias, Maluc, Hatus,
Amariah, Malluki, Hattusi,
3 Secanías, Rehum, Meremot,
Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
4 Ido, Gineto, Abias,
Iddo, Ginetoni, Abijah,
5 Mijamin, Maadias, Bilga,
Mijamini, Moadiah, Bilgah,
6 Semaías, y Joiarib, Jedaías.
Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
7 Salu, Amoc, Hilcias, Jedaias. Estos fueron los jefes de los sacerdotes y de sus hermanos en los días de Josué.
Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
8 Y los levitas: Josué, Binuy, Cadmiel, Serebias, Judá, y Matanias, que estaban encargados de la accion de gracias, él y sus hermanos.
Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
9 Y Bacbuquias y Uni, sus hermanos, estaban frente a ellos para el desempeño de sus guardas.
Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
10 Y Josué fue el padre de Joiacim, y Joiacim fue el padre de Eliasib, y Eliasib fue el padre de Joiada.
Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
11 Y Joiada fue el padre de Johanan, y Johanan fue el padre de Jadua.
Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
12 Y en los días de Joacim había sacerdotes, jefes de familia: de Seraías, Meraías; de Jeremías, Hananías;
Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
13 De Esdras, Mesululam; de Amarias, Johanán;
ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
14 De Malicu, Jonatán; de Sebanías, José;
ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
15 De Harim, Adna; de Meraiot, Helcai;
ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
16 De Ido, Zacarías; de Gineton, Mesulam;
ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
17 De Abías, Zicri; de Miniamin, de Moadias, Piltai;
ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
18 De Bilga, Samua; de Semaías, Jonatan;
ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
19 Y de Joiarib, Matenai; de Jedaias, Uzi;
ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
20 De Salai, Calai; de Amoc, Eber;
ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
21 De Hilcías, Hasabías; de Jedaias, Natanael.
ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
22 Los levitas en los días de Eliasib, Joiada, Johanan y Jadua, fueron catalogados como jefes de familia; y los sacerdotes, cuando Darío el persa era rey.
Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
23 Los hijos de Leví, jefes de familia, fueron registrados en el libro de las crónicas, incluso hasta los días de Johanán, el hijo de Eliasib.
Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
24 Y los jefes de los levitas: Hasabías, Serebias y Josué, el hijo de Cadmiel, con sus hermanos frente a ellos, para bendecir y alabar a Dios según lo ordenó David, el hombre de Dios, durante su respectivo turno de servicio.
Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
25 Matanias, y Bacbuquias, Obadias, Mesulam, Talmon, Acub, eran porteros que vigilaban las puertas de los almacenes.
Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
26 Estos fueron en los días de Joacim, el hijo de Josué, el hijo de Josadac, y en los días de Nehemías el gobernador y Esdras el sacerdote, el escriba.
Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
27 Y cuando llegó el momento de santificar el muro de Jerusalén, enviaron a los levitas de todos sus lugares para que vinieran a Jerusalén, para celebrar la fiesta de dedicación y acción de gracias con alegría, con alabanza y melodía, con címbalos, arpas y liras.
Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
28 Y los hijos de los cantores se reunieron desde las tierras bajas alrededor de de las aldeas de los netofatitas,
A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
29 Y de Bet-gilgal y de los campos de Geba y Azmavet: porque los cantores habían hecho aldeas alrededor de Jerusalén.
láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
30 Y los sacerdotes y los levitas se purificaron; e hicieron purificar a la gente, y las puertas de la ciudad y la muralla.
Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
31 Entonces hice que los gobernantes de Judá subieran a la muralla, y puse en posición dos grandes bandas de ellos que alababan, caminando en líneas ordenadas; uno fue a la derecha en la pared, en dirección a la puerta donde se colocaron los desechos;
Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
32 Y después de ellos fueron Osaias y la mitad de los gobernantes de Judá.
Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
33 Y Azarías, Esdras y Mesulam,
àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
34 Judá y Benjamín y Semaías y Jeremías,
Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
35 Y algunos de los hijos de los sacerdotes con instrumentos de viento; Zacarías, hijo de Jonatán, hijo de Semaías, hijo de Matanías, hijo de Micaías, hijo de Zacur, hijo de Asaf,
pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
36 Y sus hermanos, Semaías, y Azarel, Milalai, Gilalai, Maai, Natanael, Juda y Hanani, con los instrumentos musicales de David, el hombre de Dios; y Esdras el escriba estaba a la cabeza;
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
37 Y junto a la entrada de la fuente y directamente delante de ellos, subieron por los escalones de la ciudad de David, en la pendiente de la pared, sobre la casa de David, hasta la puerta del Agua hacia el este.
Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
38 Y la otra banda de los que alababan iba a la izquierda, y yo fui tras ellos con la mitad de la gente, en la pared, sobre la torre de los hornos, hasta la pared ancha;
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
39 Y sobre la puerta de Efraín y junto a la puerta vieja y la puerta de los Peces y la torre de Hananeel y la torre de los Cien, hasta la puerta de las Ovejas: y en la puerta de los Guardias se detuvieron.
kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
40 Así que las dos bandas de los que dieron alabanza tomaron sus posiciones en el templo de Dios, y yo y la mitad de los jefes conmigo:
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
41 Y los sacerdotes; Eliacim, Maaseias, Miniamin, Micaias, Elioenai, Zacarías, y Hananias, con instrumentos de viento;
àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
42 Y Maasias y Semaías y Eleazar y Uzi y Johanan y Malquias y Elam y Ezer. Y los cantores, supervisados por Jezrahiah, alzaron sus cantos en voz alta.
Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
43 Y aquel día hicieron grandes ofrendas y se alegraron; porque Dios los había alegrado con gran gozo; y las mujeres y los niños se alegraron con ellos, de modo que la alegría de Jerusalén llegó a oídos de los que estaban lejos.
Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
44 Y ese día pusieron a algunos hombres sobre las habitaciones donde estaban almacenadas las cosas que habían sido dadas, por las ofrendas y los primeros frutos y las décimas, que conforme a la ley llegaban las cantidades, de los campos de Cada pueblo, fijado por la ley para los sacerdotes y los levitas, porque Judá se alegró a causa de los sacerdotes y los levitas que estaban en sus lugares.
Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
45 Y ellos guardaban la ordenanza de la purificación y culto a su Dios, y fueron responsables de purificar las cosas, y también lo hicieron los cantores y los encargados de las puertas, como lo ordenaron David y Salomón, su hijo.
Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
46 Porque en los días de David y Asaf en el pasado, había un maestro de la música, de cantos de agradecimiento y alabanza a Dios.
Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
47 Y todo Israel en los días de Zorobabel y en los días de Nehemías dio lo que necesitaban a los cantores y los encargados de las puertas día tras día: e hicieron santos los ofrecimientos para los levitas; y los levitas hicieron lo mismo con los hijos de Aarón.
Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.

< Nehemías 12 >