< Josué 21 >

1 Entonces los jefes de las familias de los levitas se acercaron al sacerdote Eleazar y a Josué, hijo de Nun, y a los jefes de las familias de las tribus de los hijos de Israel;
Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
2 Y les dijeron en Silo, en la tierra de Canaán: El Señor ordenó a Moisés que tuviéramos pueblos para vivir, con sus pastizales para nuestro ganado.
Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
3 Y los hijos de Israel de su herencia dieron a los levitas estas ciudades con sus pastizales, por orden del Señor.
Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
4 Y salió la heredad de las familias de los Coats: los hijos del sacerdote Aarón, que eran de los levitas, recibieron trece ciudades de las tribus de Judá, Simeón y Benjamín.
Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
5 El resto de los hijos de Coat por sus familias recibieron diez ciudades de las tribus de Efraín y Dan y la media tribu de Manasés.
Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
6 A los hijos de Gersón de sus familias se les dio trece ciudades de las tribus de Isacar y Aser y Neftalí y la media tribu de Manasés que estaba en Basán.
Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
7 Los hijos de Merari por sus familias recibieron doce ciudades de las tribus de Rubén y Gad y Zabulón.
Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
8 Todos estos pueblos con sus pastizales los hijos de Israel dieron por decisión del Señor a los levitas, como el Señor había dado las órdenes de Moisés.
Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
9 De las tribus de los hijos de Judá y de los hijos de Simeón dieron estos pueblos, enumerados aquí por nombre:
Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
10 Estos fueron para los hijos de Aarón entre las familias de los Coatitas, de los hijos de Leví, porque fueron los primeros en la distribución.
(ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
11 Les dieron a Quiriat-arba, la ciudad de Arba, el padre de Anac, que es Hebrón en la región montañosa de Judá, con sus pastizales.
Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
12 Pero el campo abierto alrededor de la ciudad, y sus aldeas, le dieron a Caleb, el hijo de Jefone, como su propiedad.
Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
13 Y a los hijos del sacerdote Aarón dieron a Hebrón con sus pastizales, la ciudad donde el que tomaba la vida podría estar a salvo, Libna con sus pastizales;
Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
14 Jatir con sus pastizales, Estemoa con sus pastizales;
Jattiri, Eṣitemoa,
15 Holón con sus pastizales, Debir con sus pastizales;
Holoni àti Debiri,
16 Ain, y Juta, y Bet-semes, con sus pastizales; Nueve pueblos de esas dos tribus.
Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
17 Y de la tribu de Benjamín dieron Gabaón y Geba con sus pastizales;
Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
18 Anatot y Almón con sus pastizales, cuatro pueblos.
Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
19 Trece ciudades con sus pastizales fueron entregadas a los hijos de Aarón, los sacerdotes.
Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
20 El resto de las familias de los hijos de Coat, los levitas, recibieron ciudades de la tribu de Efraín.
Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
21 Y les dieron a Siquem con sus pastizales en la región montañosa de Efraín, la ciudad donde el que tomaba la vida podría estar a salvo, y Gezer con sus pastizales;
Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
22 Kibsaim y Bet-horon con sus pastizales, cuatro pueblos.
Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
23 Y de la tribu de Dan, Elteque y Gibeton con sus pastizales;
Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
24 Ajalón y Gat-Rimón con sus pastizales, cuatro pueblos.
Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
25 Y de la media tribu de Manasés, Taanac y Gat-rimon con sus praderas, dos ciudades.
Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
26 Todos los pueblos del resto de las familias de los hijos de Coat eran diez con sus pastizales.
Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
27 Y ​​a los hijos de Gersón, de las familias de los levitas, les dieron de la media tribu de Manasés, Golán en Basán con sus pastizales, la ciudad donde el que toma la vida podría estar a salvo, y Beestera con Sus pastizales, dos pueblos.
Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
28 Y de la tribu de Isacar, Cison, Daberat con sus pastizales;
Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
29 Jarmut, En-ganim con sus pastizales, cuatro pueblos.
Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
30 Y de la tribu de Aser, Misael y Abdón, con sus pastizales:
Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
31 Helcat y Rehob con sus pastizales, cuatro pueblos.
Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
32 Y de la tribu de Neftalí, Cedes en Galilea con sus pastizales, la ciudad donde el que toma la vida podría estar a salvo, y Hamot -dor y Cartan con sus pastizales, tres ciudades.
Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
33 Todos los pueblos de los gersonitas con sus familias eran trece con sus praderas.
Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
34 Y al resto de los levitas, es decir, a las familias de los hijos de Merari, les dieron de la tribu de Zabulón, Jocneam y Carta con sus pastizales;
Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
35 Dimna y Naalal con sus pastizales, cuatro pueblos.
Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
36 Y de la tribu de Rubén, Bezer y Jahaza con sus pastizales;
Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
37 Cademot y Mefaat con sus pastizales, cuatro pueblos.
Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
38 de la tribu de Gad, Ramot en Galaad, la ciudad donde el que toma la vida podría estar a salvo, y Mahanaim con sus pastizales;
Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
39 Hesbón y Jazer con sus pastizales, cuatro pueblos.
Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
40 Todos estos pueblos fueron dados a los hijos de Merari por sus familias, es decir, el resto de las familias de los levitas; y su patrimonio fue doce pueblos.
Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
41 Todas las ciudades de los levitas, entre la herencia de los hijos de Israel, eran cuarenta y ocho ciudades con sus pastizales.
Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
42 Cada uno de estos pueblos tenía pastizales a su alrededor.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
43 Y él Señor dio a Israel toda la tierra que hizo con juramento a sus padres; Así se convirtió en su patrimonio y su lugar de vida.
Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
44 Y el Señor les dio paz por todas partes, como había dicho a sus padres: todos los que estaban contra ellos se rindieron ante ellos, porque el Señor los entregó a todos en sus manos.
Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
45 Ni una sola palabra quedó sin cumplirse, en la casa de Israel sobre todo el bien que él Señor dijo que haría por ellos, y todas sus palabras se hicieron realidad.
Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.

< Josué 21 >