< Josué 12 >
1 Estos son los reyes de la tierra a quienes vencieron los hijos de Israel, tomando como herencia su tierra en el lado este del Jordán, desde el valle del Arnón hasta el Monte Hermón, y toda la región al este del Jordán:
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
2 Sehón, rey de los amorreos, que vivía en Hesbón, gobernaba desde Aroer, que se encuentra en el borde del valle del Arnón, y la ciudad en el centro del valle, y la mitad de Galaad, hasta el río Jaboc, los límites de los hijos de Amón;
Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
3 Y el Arabá al mar de Cineret, al este, y al mar del Arabá, que es el Mar Salado, al este, el camino a Bet-jesimot; y al sur, bajo las laderas de Pisga:
Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
4 Y la tierra de Og, rey de Basán, del resto de los Refaitas, que vivía en Astarot y en Edrei,
Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
5 Gobernando en la montaña de Hermón, y en Salca, y en todo Basán, hasta los límites de Gesur y Maaca, y la mitad de Galaad, a la tierra de Sehón, rey de Hesbón.
Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
6 Moisés, y los hijos de Israel los vencieron; a estos reyes y Moisés, el siervo del Señor, dio su tierra como herencia a los rubenitas, y a los gaditas, y a la media tribu de Manasés.
Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
7 Y estos son los reyes de la tierra que Josué y los hijos de Israel vencieron en el lado oeste del Jordán, desde Baal-gad en el valle del Líbano hasta el monte Halac, que sube hacia Seir; y Josué dio la tierra a las tribus de Israel por herencia, de acuerdo con sus divisiones;
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
8 En la región montañosa, en las tierras bajas, del río Jordán, en las laderas de las montañas, en las tierras baldías y en el sur; los hititas, los amorreos y los cananeos, los ferezeos, los heveos y los jebuseos.
ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
9 El rey de Jericó, uno; el rey de Hai, que está cerca de Bet-el,
Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
10 El rey de Jerusalén, el rey de Hebrón,
ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
11 El rey de Jarmut, el rey de Laquis,
ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
12 El rey de Eglón, el rey de Gezer,
ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
13 El rey de Debir, el rey de Geder,
ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
14 El rey de Horma, el rey de Arad,
ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
15 El rey de Libna, el rey de Adulam,
ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
16 El rey de Maceda, el rey de Bet-el,
ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
17 El rey de Tapua, uno; el rey de Hefer,
ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
18 El rey de Afec, el rey de Saron,
ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
19 El rey de Madon, el rey de Hazor,
ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
20 El rey de Simron-meron, el rey de Acsaf,
ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
21 El rey de Taanac, el rey de Megiddo,
ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
22 El rey de Cades, el rey de Jocneam en el Carmelo,
ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
23 El rey de Dor en la colina de Dor, uno; el rey de Goim en Gilgal,
ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
24 El rey de Tirsa, uno; Todos los reyes juntos fueron treinta y uno.
ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.