< Job 17 >
1 Mi espíritu está quebrado, mis días han terminado, el sepulcro está listo para mí.
“Ẹ̀mí mi bàjẹ́, ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú, isà òkú dúró dè mí.
2 En verdad, los que se burlan, están a mi alrededor, y mis ojos continúan viendo su amarga risa.
Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi, ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
3 Pon ahora tu fiador; porque no hay otro que ponga su mano en la mía.
“Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́; ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
4 Guardaste sus corazones de la sabiduría; por esta razón no les darás honor.
Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye; nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
5 En cuanto al que es falso a su amigo por una recompensa, la luz se cortará de los ojos de sus hijos.
Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè, òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
6 Me ha hecho vergüenza a los pueblos; y que me escupan en la cara.
“Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn; níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
7 Mis ojos se han oscurecido debido a mi dolor, y todo mi cuerpo es como una sombra.
Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́, gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
8 Los rectos se sorprenden de esto, y el que no ha hecho nada malo se levantará contra él hipócrita.
Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí, ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
9 Todavía los rectos mantendrán su camino, y el que tiene las manos limpias obtiene nuevas fuerzas.
Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú, àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
10 Pero regresen, ahora, todos ustedes, vengan; y no hallaré en ustedes a un hombre sabio.
“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín, ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí; èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
11 Mis días han pasado, mis propósitos se han roto, incluso los deseos de mi corazón.
Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá, àní ìrò ọkàn mi.
12 Están cambiando la noche en día; Dicen: La luz está cerca de la oscuridad.
Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán; wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
13 Si estoy esperando el sepulcro como mi casa, si he hecho mi cama en la oscuridad; (Sheol )
Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi; mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn. (Sheol )
14 Si digo al sepulcro: Tú eres mi padre; y al gusano, mi madre y mi hermana;
Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi, àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
15 ¿Dónde está mi esperanza? ¿Y quién verá mi deseo?
ìrètí mi ha dà nísinsin yìí? Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
16 ¿Bajarán conmigo al inframundo? ¿Descansaremos juntos en polvo? (Sheol )
Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú, nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?” (Sheol )