< Jeremías 50 >

1 La palabra que el Señor dijo acerca de Babilonia, sobre la tierra de los caldeos, por el profeta Jeremías.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 Proclámalo entre las naciones, hazlo público y deja que se levante bandera; da la palabra y no guardes nada; digamos: Babilonia está tomada, Bel está avergonzado, Merodac está destrozado, sus imágenes son destruidas, sus dioses están quebrados.
“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 Porque desde el norte una nación se enfrenta a ella, lo que hará que su tierra sea arruinada y un desierto; están huyendo, el hombre y la bestia se han ido.
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
4 En aquellos días y en ese tiempo, dice el Señor, vendrán los hijos de Israel, ellos y los hijos de Judá juntos; ellos seguirán su camino llorando y buscando al Señor su Dios.
“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
5 Se preguntarán sobre el camino a Sión, con los rostros girados en su dirección, diciendo: Ven, y únete al Señor en un acuerdo eterno que se tendrá en cuenta para siempre.
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
6 Mi pueblo ha sido ovejas errantes; sus pastores los han hecho ir por el camino equivocado, dejándolos sueltos en las montañas; han ido de montaña a colina, sin tener memoria de su lugar de descanso.
“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 Fueron atacados por todos aquellos que se cruzaron con ellos; y sus atacantes dijeron: No estamos haciendo nada malo, porque han hecho lo malo contra el Señor en quien está la justicia, contra el Señor, la esperanza de sus padres.
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
8 Huyan de Babilonia, salgan de la tierra de los caldeos, y como los cabríos que van delante del rebaño.
“Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
9 Porque mira, me estoy moviendo y enviando a Babilonia una multitud de grandes naciones del país del norte; y pondrán sus ejércitos en posición contra ella; y de allí será tomada; sus flechas serán como las de un experto en guerra; Nadie volverá en vano.
Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
10 Y la riqueza de Caldea caerá en manos de sus atacantes; todos los que la tomen tendrán suficiente, dice el Señor.
A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
11 Porque te alegras, porque te regocijas, destruyendo mi herencia, porque juegas como una novilla, y relinchas como caballo;
“Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Tu madre será avergonzada; La que te dio a luz será despreciada; mira, ella será la última de las naciones, un lugar desolado, una tierra seca y sin agua.
Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 Debido a la ira del Señor, nadie vivirá en ella, y estará completamente asolada; todos los que pasen por Babilonia serán asombrados, y silbará sobre todas sus plagas.
Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
14 Pon tus ejércitos en posición contra Babilonia por todos lados, todos ustedes arqueros; suelten sus flechas hacia ella, sin retroceder, porque ella ha hecho el mal contra el Señor.
“Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Da un grito fuerte contra ella por todos lados; ella se ha entregado a sí misma, sus cimientos están caídos, sus muros están derribados; porque esta es la venganza del Señor; tomen venganza de ella; como ella lo ha hecho, así hazle a ella.
Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Que él sembrador de semillas sea destruido de Babilonia, y todos los que usen la hoz en el momento del corte de grano; por temor a la espada destructora, todos se dirigirán a su pueblo, todos huirán a su tierra.
Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Israel es una oveja errante; los leones lo han dispersado; primero fue devorado por el rey de Asiria, y ahora sus huesos fueron rotos por Nabucodonosor, rey de Babilonia.
“Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
18 Esto es lo que ha dicho el Señor de los ejércitos, el Dios de Israel: Mira, enviaré castigo al rey de Babilonia y a su tierra, como lo he castigado al rey de Asiria.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 Haré que Israel regrese a su lugar de descanso, y pastará en Carmel y Basán, y saciará su alma extensión en las colinas de Efraín y en Galaad.
Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
20 En aquellos días y en ese tiempo, dice el Señor, cuando se busque el mal de Israel, no habrá nada; y en Judá no se verán pecados, porque tendré perdón para aquellos a quienes guardaré.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
21 Sube contra la tierra de Merataim, contra esta, y contra la gente de Pecod; mata y envía destrucción tras ellos, dice el Señor, y haz todo lo que te he ordenado que hagas.
“Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 Hay un sonido de guerra en la tierra y de gran destrucción.
Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 ¡Cómo ha sido cortado y quebrado el martillo de toda la tierra en dos! ¿Cómo se ha convertido Babilonia en desolación entre las naciones?
Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 He puesto una red para ti, y has sido tomada, oh Babilonia, sin que lo supieras; has sido encontrada y presa porque provocaste al Señor.
Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 Desde su almacén, el Señor ha tomado los instrumentos de su ira; porque el Señor, el Señor de los ejércitos, tiene una obra que hacer en la tierra de los caldeos.
Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Ve contra ella todos y cada uno, deja que sus almacenes se abran; conviértela en una masa de piedras, destrúyela por completo, hasta que no se vea nada de ella.
Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Pon todos sus bueyes a la espada; Que bajen a la muerte; el dolor es de ellos, porque ha llegado su día, el tiempo de su castigo.
Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 La voz de los que están huyendo, que se han escapado a salvo de la tierra de Babilonia, para dar noticias en Sion del castigo del Señor nuestro Dios, la venganza de su Templo.
Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
29 Envía a los arqueros a unirse contra Babilonia, todos los arqueros; levanten sus tiendas contra ella por todos lados; que nadie se escape; dale la recompensa de su trabajo; como ella ha hecho, así también a ella; porque ha sido exaltada de orgullo contra el Señor, contra el Santo de Israel.
“Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Por esta causa sus jóvenes caerán en sus calles, y todos sus hombres de guerra serán destruidos en ese día, dice el Señor.
Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
31 Mira, estoy contra ti, oh soberbio, dice el Señor, el Señor de los ejércitos, porque ha llegado tu día, el momento en que te enviaré el castigo.
“Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 Y el soberbio irá con pasos inciertos y tendrá una caída, y no habrá nadie que venga a ayudarlo; y pondré fuego en sus pueblos, quemando todo a su alrededor.
Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
33 Esto es lo que ha dicho el Señor de los ejércitos: Los hijos de Israel y los hijos de Judá son oprimidos juntos; todos los que los tomaron prisioneros los mantienen retenidos; No los dejarán ir.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Su salvador es fuerte. El Señor de los ejércitos es su nombre; ciertamente tomará su causa, para que pueda dar descanso a la tierra y problemas a la gente de Babilonia.
Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
35 Hay una espada en los caldeos, dice el Señor, y en el pueblo de Babilonia, en sus gobernantes y en sus sabios.
“Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 Hay una espada contra los adivinos, y se volverán tontos; una espada contra sus hombres de guerra, y serán quebrantados.
Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Hay una espada sobre todos los extranjeros que hay en ella, y se volverán como mujeres; una espada sobre sus almacenes, y serán tomados por sus atacantes.
Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Una espada está sobre sus aguas, secándolas; porque es una tierra de imágenes, y se vuelven locos por dioses falsos.
Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
39 Por esta razón, las bestias de la tierra baldía con los lobos harán sus agujeros allí y los avestruces vivirán en ella; nunca más los hombres vivirán allí, será poblada de generación en generación.
“Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Como cuando Sodoma y Gomorra y sus pueblos vecinos fueron derrocados por Dios, dice el Señor, así ningún hombre vivirá en ella, y ningún hijo de hombre tendrá un lugar de descanso allí.
Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
41 Mira, viene un pueblo del norte; una gran nación y una serie de reyes serán puestos en movimiento desde las partes más internas de la tierra.
“Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Arcos y lanzas están en sus manos; son crueles y no tienen piedad; su voz es como el trueno del mar, y van sobre caballos; Todos en su lugar, como hombres que van a pelear, contra ti, hija de Babilonia.
Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 El rey de Babilonia ha tenido noticias de ellos, y sus manos se han debilitado; le han llegado problemas y dolor como el dolor de una mujer en el parto.
Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Mira, él subirá como un león desde el espeso crecimiento del Jordán contra el lugar de descanso de Temán; pero de repente los haré huir de ella; y pondré sobre ella al hombre de mi elección, ¿quién es como yo? ¿Y quién presentará su causa contra mí? ¿Y qué guardián de ovejas mantendrá su lugar delante de mí?
Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
45 Escuchen la decisión del Señor que tomó contra Babilonia, y sus propósitos diseñados contra la tierra de los caldeos; En verdad, serán arrastrados por el rebaño más pequeño; En verdad, hará desperdiciar sus campos con ellos.
Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
46 Al grito, ¡Babilonia es tomada! la tierra tiembla, y el clamor llega a los oídos de las naciones.
Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Jeremías 50 >