< Isaías 19 >

1 La palabra acerca de Egipto. Mira, el Señor está sentado en una nube que se mueve rápidamente y viene a Egipto, y los falsos dioses de Egipto se estremecen con su venida, y el corazón de Egipto se derrite dentro de ellos.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Ejibiti. Kíyèsi i, Olúwa gun àwọsánmọ̀ tí ó yára lẹ́ṣin ó sì ń bọ̀ wá sí Ejibiti. Àwọn ère òrìṣà Ejibiti wárìrì níwájú rẹ̀, ọkàn àwọn ará Ejibiti sì ti domi nínú wọn.
2 Y enviaré a los egipcios contra los egipcios; y pelearán cada uno contra su hermano, y cada uno contra su prójimo; pueblo contra pueblo, y reino contra reino.
“Èmi yóò rú àwọn ará Ejibiti sókè sí ara wọn arákùnrin yóò bá arákùnrin rẹ̀ jà, aládùúgbò yóò dìde sí aládùúgbò rẹ̀, ìlú yóò dìde sí ìlú, ilẹ̀ ọba sí ilẹ̀ ọba.
3 Y el espíritu de Egipto será desanimado en el, y confundiré sus planes; y se volverán a los dioses falsos, a los brujos, a los que tienen control de los espíritus de los muertos, a los adivinos.
Àwọn ará Ejibiti yóò sọ ìrètí nù, èmi yóò sì sọ èrò wọn gbogbo di òfo; wọn yóò bá àwọn òrìṣà àti ẹ̀mí àwọn òkú sọ̀rọ̀, àwọn awoṣẹ́ àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀.
4 Y entregaré a los egipcios en manos de un amo cruel; y un rey duro será su gobernante, dice el Señor, el Señor de los ejércitos.
Èmi yóò fi Ejibiti lé agbára àwọn ìkà amúnisìn lọ́wọ́, ọba aláìláàánú ni yóò jẹ ọba lé wọn lórí,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 Y las aguas del mar serán cortadas, y el río se secará y se desechará.
Gbogbo omi inú odò ni yóò gbẹ, gbogbo ilẹ̀ àyíká odò ni yóò gbẹ tí yóò sì sáàpá.
6 Y los ríos tendrán mal olor. La corriente de Egipto se volverá pequeña y seca: todas las plantas acuáticas quedarán en nada.
Adágún omi yóò sì di rírùn; àwọn odò ilẹ̀ Ejibiti yóò máa dínkù wọn yóò sì gbẹ. Àwọn koríko odò àti ìrẹ̀tẹ̀ yóò gbẹ,
7 Las tierras de pastoreo junto al Nilo, y todo lo plantado por el Nilo, se secarán, o se quitarán por el viento, y terminarán.
àwọn igi ipadò Naili pẹ̀lú, tí ó wà ní orísun odò, gbogbo oko tí a dá sí ipadò Naili yóò gbẹ dànù tí yóò sì fẹ́ dànù tí kò sì ní sí mọ́.
8 Los pescadores estarán tristes, y todos los que ponen líneas de pesca en el Nilo estarán llenos de pena, y aquellos cuyas redes se extienden sobre las aguas tendrán dolor en sus corazones.
Àwọn apẹja yóò sọkún kíkorò, àti gbogbo àwọn tí ó ń ju ìwọ̀ sínú odò; odò náà yóò sì máa rùn.
9 Y serán decepcionados todos los trabajadores de hilo de lino, y los que hacen tela de algodón.
Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ yóò kọminú àwọn ahunṣọ ọ̀gbọ̀ yóò sọ ìrètí nù.
10 Y los que hacen redes serán rotas, y los que hacen viveros para peces serán entristecidos.
Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ aṣọ yóò rẹ̀wẹ̀sì, gbogbo àwọn oníṣẹ́ oṣù ni àìsàn ọkàn yóò ṣe.
11 Los jefes de Zoan son completamente necios; los guías más sabios de Faraón se han convertido en bestias: ¿cómo le dices a Faraón que soy hijo de los sabios, descendencia de los primeros reyes?
Àwọn oníṣẹ́ Ṣoani ti di aláìgbọ́n, àwọn ọlọ́gbọ́n olùdámọ̀ràn Farao ń mú ìmọ̀ràn àìgbọ́n wá. Báwo ló ṣe lè sọ fún Farao pé, “Mo jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn ọba àtijọ́.”
12 ¿Dónde están tus sabios? Deja que te lo expliquen, que te den conocimiento del propósito del Señor de los ejércitos para Egipto.
Níbo ni àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn rẹ wà báyìí? Jẹ́ kí wọn fihàn ọ́ kí wọn sì sọ ọ́ di mí mọ̀ ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pinnu lórí Ejibiti.
13 Los jefes de Zoán se han vuelto insensatos, los jefes de Menfis, son engañados, los jefes de sus tribus son la causa de que Egipto se haya alejado del camino.
Àwọn ọmọ-aládé Ṣoani ti di aṣiwèrè, a ti tan àwọn ọmọ-aládé Memfisi jẹ; àwọn òkúta igun ilé tí í ṣe ti ẹ̀yà rẹ ti ṣi Ejibiti lọ́nà.
14 El Señor ha enviado entre ellos un espíritu de error: y para ellos, Egipto se desvía de la manera correcta en todas sus acciones, ya que un hombre vencido por el vino es incierto en sus pasos.
Olúwa ti da ẹ̀mí òòyì sínú wọn; wọ́n mú Ejibiti ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú ohun gbogbo tí ó ń ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọ̀mùtí ti í ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú èébì rẹ̀.
15 Y en Egipto no habrá trabajo para ningún hombre, cabeza o cola, alto o bajo, para hacer.
Kò sí ohun tí Ejibiti le ṣe— orí tàbí ìrù, ọ̀wá ọ̀pẹ tàbí koríko odò.
16 En ese día, los egipcios serán como mujeres: y la tierra se estremecerá de temor por la agitación de la mano del Señor extendida sobre ella.
Ní ọjọ́ náà ni àwọn ará Ejibiti yóò dàbí obìnrin. Wọn yóò gbọ̀n jìnnìjìnnì pẹ̀lú ẹ̀rù nítorí ọwọ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí a gbé sókè sí wọn.
17 Y la tierra de Judá será causa de gran temor para Egipto; siempre que su nombre venga a la mente, Egipto tendrá miedo ante el Señor de los ejércitos debido a su propósito contra él.
Ilẹ̀ Juda yóò sì di ẹ̀rù fún Ejibiti; gbogbo àwọn tí a bá ti dárúkọ Juda létí wọn ni yóò wárìrì, nítorí ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbèrò láti ṣe sí wọn.
18 En ese día habrá cinco pueblos en la tierra de Egipto usando el lenguaje de Canaán y haciendo juramentos al Señor de los ejércitos; y uno de ellos se llamará, La Ciudad de destrucción.
Ní ọjọ́ náà ìlú márùn-ún ní ilẹ̀ Ejibiti yóò sọ èdè àwọn ará Kenaani, wọn yóò sì búra àtìlẹ́yìn fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Ọ̀kan nínú wọn ni a ó sì máa pè ní ìlú ìparun.
19 En aquel día habrá un altar para el Señor en medio de la tierra de Egipto, y una columna para el Señor al borde de la tierra.
Ní ọjọ́ náà pẹpẹ kan yóò wà fún Olúwa ní àárín gbùngbùn Ejibiti, àti ọ̀wọ́n kan fún Olúwa ní etí bodè rẹ̀.
20 Y será una señal y un testimonio para el Señor de los ejércitos en la tierra de Egipto: cuando clamen al Señor contra quien los oprimen, él les enviará un salvador para que los defienda y salve.
Yóò sì jẹ́ àmì àti ẹ̀rí sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ilẹ̀ Ejibiti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe Olúwa nítorí àwọn aninilára wọn, yóò rán olùgbàlà àti olùgbèjà kan sí wọn tí yóò sì gbà wọ́n sílẹ̀.
21 Y el Señor se dará a conocer a Egipto, y los egipcios le darán honor al Señor en ese día; Le rendirán culto con ofrendas y ofrendas de comida, y jurarán al Señor y le darán efecto.
Báyìí ni Olúwa yóò sọ ara rẹ̀ di mí mọ̀ fún àwọn ará Ejibiti àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò gba Olúwa gbọ́. Wọn yóò sìn ín pẹ̀lú ẹbọ ọrẹ ìyẹ̀fun, wọn yóò jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa wọn yóò sì mú un ṣẹ.
22 Y el Señor enviará castigo a Egipto, y los herirá; y cuando regresen al Señor, él escuchará su oración y les quitará la enfermedad.
Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn kan bá Ejibiti jà; yóò bá wọn jà yóò sì tún wò wọ́n sàn. Wọn yóò yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn yóò sì wò wọ́n sàn.
23 En ese día habrá una carretera de Egipto a Asiria, y Asiria vendrá a Egipto, y Egipto entrará a Asiria; y los egipcios adorarán al Señor junto con los asirios.
Ní ọjọ́ náà òpópónà kan yóò wá láti Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Asiria yóò lọ sí Ejibiti àti àwọn ará Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Ejibiti àti ará Asiria yóò jọ́sìn papọ̀.
24 En ese día, Israel será, junto, con Egipto y Asiria una bendición en medio de la tierra.
Ní ọjọ́ náà Israẹli yóò di ẹ̀kẹta pẹ̀lú Ejibiti àti Asiria, àní orísun ìbùkún ní ilẹ̀ ayé.
25 Por la bendición del Señor de los ejércitos que les ha dado, diciendo: Una bendición para Egipto, mi pueblo, y para Asiria, la obra de mis manos, y para Israel, mi herencia.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò bùkún wọn yóò wí pé, “Ìbùkún ni fún Ejibiti ènìyàn mi, Asiria iṣẹ́ ọwọ́ mi, àti Israẹli ìní mi.”

< Isaías 19 >