< Isaías 14 >
1 Porque el Señor tendrá misericordia de Jacob, y volverá a hacer de Israel su pueblo especial, y los pondrá en su tierra; y el hombre extranjero se juntara a ellos y se unirá a la familia de Jacob.
Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
2 Y el pueblo los llevará con ellos a su lugar, y los hijos de Israel les darán una herencia en la tierra del Señor como sirvientes y sirvientas, haciéndolos prisioneros de los cuales eran prisioneros; y serán gobernantes de sus amos.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
3 Y será en el día en que el Señor te dé descanso de tu dolor, de tu angustia y del duro yugo que te habían puesto.
Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
4 Que recitarás esta amarga canción contra el rey de Babilonia, y dirás: ¡Cómo ha terminado el cruel tirano! Como cesó la ciudad de oro;
ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
5 La vara de los que hacen el mal, la vara de los gobernantes, es quebrantada por el Señor;
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
6 Aquel cuya vara estaba sobre los pueblos con una ira interminable, gobernando a las naciones con ira, con un gobierno incontrolado.
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
7 Toda la tierra está en reposo y está en silencio y estalla en cantos de alegría.
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
8 Incluso los árboles del bosque se alegran sobre ti, los árboles del Líbano, diciendo: Desde el momento de tu caída, ningún cortador de madera ha subido contra nosotros con un hacha.
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
9 El inframundo se conmueve con tu venida, los muertos están despiertos ante ti, incluso los fuertes de la tierra. Todos los reyes del mundo se han levantado de sus asientos. (Sheol )
Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol )
10 Todos te responden y te dicen: ¿Te has vuelto débil como nosotros? ¿Has sido hecho como nosotros?
Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Tu orgullo ha descendido al inframundo y el ruido de tus instrumentos de música; Los gusanos están debajo de ti, y tu cuerpo está cubierto con ellos. (Sheol )
Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol )
12 ¡Qué grande es tu caída del cielo, oh lucero de la aurora, hijo de la mañana! ¿Cómo has caído a la tierra, tú que debilitabas a las naciones?
Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Porque dijiste en tu corazón: Subiré al cielo, haré mi asiento más alto que las estrellas de Dios; Tomaré mi lugar en la montaña del lugar de reunión de los dioses, en las partes más alejadas del norte.
Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Subiré más alto que las nubes; Seré como el Altísimo.
Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Pero descenderás al inframundo, incluso a sus partes más profundas. (Sheol )
Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol )
16 Los que te vean te estarán observando con cuidado, pensarán profundamente y dirán: ¿Es éste el perturbador de la tierra, el agitador de los reinos?
Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Que hizo del mundo un desperdicio, derribando sus ciudades; Quien no dejó escapar a sus prisioneros de la cárcel.
Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
18 Todos los reyes de la tierra descansan en gloria, cada uno en su sepulcro.
Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Pero tú, como un nacimiento antes de su tiempo, estás tendido sin lugar de descanso en la tierra; vestido con los cuerpos de los muertos que han sido arrojados a la espada, que descienden a las partes más bajas del inframundo; Un cuerpo muerto, aplastado bajo el pie.
Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 En cuanto a tus padres, no estarás unido a ellos en su lugar de descanso, porque has sido la causa de la destrucción de tu tierra y de la muerte de tu pueblo; la semilla del malvado no tendrá lugar en la memoria del hombre.
a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Prepara un lugar de muerte para sus hijos, por el mal hecho de sus padres; para que no puedan subir y tomar la tierra por su herencia, cubriendo la faz del mundo con ciudades.
Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
22 Porque subiré contra ellos, dice el Señor de los ejércitos, cortando el nombre y la descendencia de Babilonia, el hijo y el hijo del hijo, dice el Señor.
“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
23 Y te haré una herencia para el erizo y los estanques de agua; y la barreré con la escoba de la destrucción, dice el Señor de los ejércitos.
Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
24 El Señor de los Ejércitos ha hecho un juramento, diciendo: Lo que había pensado ciertamente se cumplirá, y lo que había planeado se llevará a cabo.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
25 Para que el asirio sea quebrantado en mi tierra, y aplastado bajo mis montañas: allí será quitado su yugo, y su gobierno sobre ellos llegará a su fin.
Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
26 Este es el propósito para toda la tierra, y esta es la mano extendida sobre todas las naciones.
Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
27 Porque es el propósito del Señor de los ejércitos, y ¿quién lo hará inútil? cuando su mano está extendida, ¿por quién puede ser devuelta?
Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
28 En el año de la muerte del rey Acaz, esta palabra llegó al profeta:
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
29 No se alegren, oh Filistea, todos ustedes, porque se quebró la vara que los oprimía; porque de la raíz de la serpiente saldrá una serpiente venenosa, y su fruto será una serpiente venenosa alada.
Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 Y los más pobres de la tierra tendrán comida, y los necesitados tendrán un lugar de descanso seguro, pero tu simiente llegará a su fin por la necesidad de comida, y el resto de ustedes serán puestos a la espada.
Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
31 ¡Envía un clamor, oh puerta! ¡Gime de tristeza, pueblo! Desanímate, tu tierra ha quedado en nada, oh Filistea; porque sale un humo del norte, y todos mantienen su lugar en la fila.
Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
32 ¿Qué respuesta dará, entonces, mi pueblo a los representantes de la nación? Que el Señor es el constructor de Sión, y ella será un lugar seguro para los pobres de su pueblo.
Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”