< Esdras 4 >
1 Llegaron noticias a los que odiaban a Judá y Benjamín, de que las personas que habían regresado estaban reconstruyendo un templo para el Señor, el Dios de Israel;
Nígbà tí àwọn ọ̀tá Juda àti Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ìgbèkùn tí ó padà dé ń kọ́ tẹmpili fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli,
2 Entonces vinieron a Zorobabel y a los jefes de familia, y les dijeron: Participemos en el edificio contigo; Porque somos siervos de tu Dios, así como tú eres; y le hemos estado haciendo ofrendas desde los días de Esar-hadon, rey de Asiria, que nos puso aquí.
wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Serubbabeli àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé, wọ́n sì wí pé, “Jẹ́ kí a bá a yín kọ́ nítorí pé, bí i tiyín, a ń wá Ọlọ́run yín, a sì ti ń rú ẹbọ sí i láti ìgbà Esarhadoni ọba Asiria, tí ó mú wa wá sí ibi yìí.”
3 Pero Zorobabel, Josué y el resto de los jefes de familia en Israel les respondieron: Tú no tienes parte con nosotros en la construcción de un templo para nuestro Dios; nosotros mismos haremos el trabajo juntos por el Señor, el Dios de Israel, como Ciro, el rey de Persia, nos ha dado órdenes.
Ṣùgbọ́n Serubbabeli, Jeṣua àti ìyókù àwọn olórí àwọn ìdílé Israẹli dáhùn pé, “Ẹ kò ní ohunkóhun pẹ̀lú wa ní kíkọ́ ilé fún Ọlọ́run wa. Àwa nìkan yóò kọ́ ọ fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, bí Kirusi, ọba Persia, ti pàṣẹ fún wa.”
4 Entonces la gente de la tierra hizo débiles las manos de la gente de Judá, atemorizándolos para que no terminaran la reconstrucción;
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú ọwọ́ àwọn ènìyàn Juda rọ, wọ́n sì dẹ́rùbà wọ́n ní ti kíkọ́ ilé náà.
5 Y sobornaron a hombres que hicieron planes contra ellos y les impidieron cumplir su propósito, durante todo el tiempo de Ciro, rey de Persia, hasta que Darío se convirtió en rey.
Wọ́n gba àwọn olùdámọ̀ràn láti ṣiṣẹ́ lòdì sí wọn àti láti sọ ète wọn di asán ní gbogbo àsìkò ìjọba Kirusi ọba Persia àti títí dé ìgbà ìjọba Dariusi ọba Persia.
6 Y en el tiempo de Asuero, cuando se convirtió en rey por primera vez, dejaron constancia de una declaración contra el pueblo de Judá y Jerusalén.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Ahaswerusi wọ́n fi ẹ̀sùn kan àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
7 Y en el tiempo de Artajerjes, Bislam, Mitrídates, Tabeel y el resto de sus amigos, enviaron una carta a Artajerjes, rey de Persia, escribiéndola en la escritura y el idioma arameos.
Àti ní àkókò ìjọba Artasasta ọba Persia, Biṣilami, Mitredati, Tabeli àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù kọ̀wé sí Artasasta. A kọ ìwé náà ní ìlànà ìkọ̀wé Aramaiki èdè Aramaiki sì ní a fi kọ ọ́.
8 Rehum, el principal gobernante, y Simsai, el escriba, enviaron una carta contra Jerusalén, al rey Artajerjes;
Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé jùmọ̀ kọ́ ìwé láti dojúkọ Jerusalẹmu sí Artasasta ọba báyìí:
9 La carta fue enviada por Rehum, el gobernante principal, y Simsai, el escriba y sus amigos; los Dineos, Aparsaqueos, Tarpelitas, Afarseos, Arqueos, Babilonios, los Susasqueos, los Dieveos, y los Elamitas,
Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn tókù—àwọn ará Dina, ti Afarsatki, ti Tarpeli, ti Afarsi, Ereki àti Babeli, àwọn ará Elamu ti Susa,
10 Y el resto de las naciones que el gran y noble Asnapar llevó desterradas y puso en Samaria y en el resto del país sobre el río:
pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn tí ẹni ọlá àti ẹni ọ̀wọ̀ Asnappari kó jáde, tí ó sì tẹ̀ wọ́n dó sí ìlú Samaria àti níbòmíràn ní agbègbè e Eufurate.
11 Esta es una copia de la carta que enviaron al rey Artajerjes: Tus siervos que viven al otro lado del río envían estas palabras:
(Èyí ni ẹ̀dà ìwé tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i.) Sí ọba Artasasta, láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin agbègbè Eufurate.
12 Le damos noticias al rey de que los judíos que vinieron de ustedes vinieron a nosotros a Jerusalén; están construyendo otra vez esa ciudad descontrolada y malvada; Las paredes están completas y están uniendo los fundamentos.
Ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé àwọn ará Júù tí ó gòkè wá sọ́dọ̀ wa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ti lọ sí Jerusalẹmu wọ́n sì ń tún ìlú búburú àti ìlú ọlọ̀tẹ̀ ẹ nì kọ́. Wọ́n ń tún àwọn ògiri náà kọ́, wọ́n sì ń tún àwọn ìpìlẹ̀ náà ṣe.
13 El rey puede estar seguro de que cuando se complete la construcción de esta ciudad y sus muros, no pagarán impuestos ni pagos en bienes o tributo, y al final será una causa de pérdida para los reyes.
Síwájú sí i, ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé tí a bá kọ́ ìlú yìí àti tí a sì tún àwọn ògiri rẹ̀ mọ, kò sí owó orí, owó òde tàbí owó ibodè tí a ó san, owó tí ó sì ń wọlé fún ọba yóò sì dínkù.
14 Ahora, porque somos responsables ante el rey, y no es correcto que veamos que se daña el honor del rey, hemos enviado para hacerlo saber al rey la palabra de estas cosas,
Nísinsin yìí níwọ̀n ìgbà tí a ní ojúṣe sí ààfin ọba, kò sì bójúmu fún wa láti rí ìtàbùkù ọba, àwa ń rán iṣẹ́ yìí láti sọ fún ọba,
15 Para que la búsqueda se haga en el libro de los registros de sus antepasados, y verás en el libro de los registros que esta ciudad ha sido descontrolada, y que causa problemas a los reyes y países, y que allí hubo arrebatos contra la autoridad allí en el pasado: por lo que la ciudad fue destruida.
kí a bá a lè ṣe ìwádìí ní inú ìwé ìrántí àwọn aṣíwájú rẹ̀. Nínú ìwé ìrántí wọn yìí, ìwọ yóò rí i wí pé, ìlú yìí jẹ́ ìlú aṣọ̀tẹ̀, oníwàhálà sí àwọn ọba àti àwọn ìgbèríko, ibi ìṣọ̀tẹ̀ láti ìgbà àtijọ́. Ìdí ni èyí tí a ṣe pa ìlú yìí run.
16 Les damos la noticia de que si la construcción de esta ciudad y sus muros se completan, habrá un fin de su poder en el país al otro lado del río.
A fi dá ọba lójú wí pé tí a bá tún ìlú kọ́ àti ti àwọn ògiri rẹ̀ si di mímọ padà, kì yóò sì ohun ti yóò kù ọ́ kù ní agbègbè Eufurate.
17 Entonces el rey envió una respuesta a Rehum, el gobernante principal, a Simsai el escriba, a sus amigos que viven en Samaria, y al resto de los que están al otro lado del río, diciéndoles: ¡Paz!
Ọba fi èsì yìí ránṣẹ́ padà. Sí Rehumu balógun, Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn yòókù tí ń gbé ní Samaria àti ní òpópónà Eufurate. Ìkíni.
18 Y ahora se me ha aclarado el sentido de la carta que nos enviaste.
A ti ka ìwé tí ẹ fi ránṣẹ́ sí wa, a sì ti túmọ̀ rẹ̀ níwájú mi.
19 Y di órdenes de que se realizará una búsqueda, y es cierto que en el pasado este pueblo causó problemas a los reyes y que allí se produjeron rebeliones contra la autoridad.
Mo pa àṣẹ, a sì ṣe ìwádìí, nínú ìtàn ọjọ́ pípẹ́ àti ti ìsinsin yìí ti ìṣọ̀tẹ̀ sí àwọn ọba pẹ̀lú, ó sì jẹ́ ibi ìṣọ̀tẹ̀ àti ìrúkèrúdò.
20 Además, ha habido grandes reyes en Jerusalén, que gobiernan todo el país al otro lado del río, a quienes se les entregan impuestos y pagos de bienes y tributos.
Jerusalẹmu ti ní àwọn ọba alágbára tí ń jẹ ọba lórí gbogbo àwọn agbègbè Eufurate, àti àwọn owó orí, owó òde àti owó ibodè sì ni wọ́n ń san fún wọn.
21 Da una orden ahora, que estos hombres no continúen, y que la construcción de la ciudad debe ser detenida, hasta que yo dé una orden.
Nísinsin yìí pa àṣẹ fún àwọn ọkùnrin yìí láti dá iṣẹ́ dúró, kí a má ṣe tún ìlú náà kọ títí èmi yóò fi pàṣẹ.
22 Asegúrate de hacer esto con todo cuidado; no permitas que los problemas aumenten para perjuicio de los reyes.
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe àìkọbi-ara sí ọ̀rọ̀ yìí. Èéṣe tí ìbàjẹ́ yóò fi pọ̀ sí i, sí ìpalára àwọn ọba?
23 Luego, después de leer la carta del rey, Rehum y Simsai, el escriba y sus amigos fueron rápidamente a Jerusalén, a los judíos, y los hicieron detener la reconstrucción por la fuerza.
Ní kété tí a ka ẹ̀dà ìwé ọba Artasasta sí Rehumu àti Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, wọ́n yára lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, wọ́n fi agbára mú wọn láti dáwọ́ dúró.
24 Así de está manera fue la obra del templo de Dios en Jerusalén; así se detuvo, hasta el segundo año del gobierno de Darío, rey de Persia.
Báyìí, iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu wá sí ìdúró jẹ́ẹ́ títí di ọdún kejì ìjọba Dariusi ọba Persia.