< Esdras 10 >

1 Mientras Esdras hacía su oración y su confesión, lloraba y arrodillado ante él templo de Dios, un gran número de hombres, mujeres y niños de Israel se reunieron a su alrededor; porque la gente lloraba. amargamente.
Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
2 Entonces Secanias, hijo de Jehiel, uno de los hijos de Elam, respondiendo, dijo a Esdras: Hemos hecho lo malo contra nuestro Dios, y hemos tomado como esposas a mujeres extranjeras de los pueblos de la tierra; sin embargo todavía hay esperanza para Israel a pesar de esto.
Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
3 Hagamos ahora un acuerdo con nuestro Dios para despedir a todas las esposas y a todos sus hijos, si le parece correcto a mi señor y a los que temen las palabras de nuestro Dios; y que se haga conforme a la ley.
Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
4 ¡Arriba, ahora! pues esto es asunto tuyo, y estamos contigo; Anímate y hazlo.
Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
5 Entonces Esdras se levantó e hizo que los jefes de los sacerdotes y los levitas y todo Israel juraran que harían esto. Así que hicieron un juramento.
Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
6 Esdras se levantó de la casa de Dios y entró en la habitación de Johanán, el hijo de Eliasib; pero cuando llegó allí, no comió ni bebió, porque lamentaba el pecado de los que habían regresado del destierro.
Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
7 E hicieron una declaración pública por medio de todo Judá y Jerusalén, a todos los que habían regresado del destierro, que debían venir juntos a Jerusalén;
Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
8 Y que si alguien no llegaba antes de que pasaran los tres días, como lo ordenaron los gobernantes y los hombres responsables, todos sus bienes serían sometidos a la maldición, y él mismo sería separado de la comunidad de la gente, de los que volvieron del destierro.
Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
9 Entonces todos los hombres de Judá y Benjamín se reunieron en Jerusalén antes de que pasaran los tres días; fue el noveno mes, a los veinte días del mes; y todas las personas estaban sentadas en la amplia plaza frente a la casa de Dios, temblando de miedo por este asunto y por la gran lluvia.
Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
10 Y el sacerdote Esdras se puso de pie y les dijo: Has hecho mal y has tomado mujeres extranjeras por esposas, aumentando así el pecado de Israel.
Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
11 Ahora, alaba al Señor, el Dios de tus padres, y haz su placer; y sepárense de los pueblos de la tierra y de las mujeres extranjeras.
Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
12 Entonces todas las personas, respondiendo, dijeron en voz alta: Como usted ha dicho, así es correcto que hagamos.
Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
13 Pero la cantidad de gente es grande, y es tiempo de mucha lluvia; No es posible que sigamos esperando afuera, y esto no es algo que se pueda hacer en un día o incluso dos: porque nuestro pecado en este negocio es grande.
Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
14 Ahora, que nuestros gobernantes sean representantes de todas las personas, y que todos los que están casados con mujeres extranjeras en nuestros pueblos vengan a horas fijas, y con ellos los hombres responsables y los jueces de cada pueblo, hasta que la ardiente ira de nuestro Dios se aparte de nosotros.
Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
15 Sólo Jonatán, el hijo de Asael, y Jahazias, el hijo de Ticva, estaban en contra de esto, Mesulam y Sabetai el levita que los apoyaban.
Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
16 Así que los que habían regresado lo hicieron. Y el sacerdote Esdras, con ciertos jefes de familia, por las familias de sus padres, todos ellos por sus nombres, fueron escogidos; y el primer día del décimo mes tomaron sus lugares para abordar la cuestión con cuidado.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
17 Y llegaron al final de todos los hombres que estaban casados con mujeres extranjeras el primer día del primer mes.
ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
18 Y entre los hijos de los sacerdotes que estaban casados con mujeres extranjeras estaban estos: de los hijos de Josué, el hijo de Josadac y sus hermanos, Maasias y Eliezer y Jarib y Gedalías.
Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
19 Y dieron su palabra de que iban a despedir a sus esposas; y por su pecado, dieron una ofrenda de un carnero.
Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
20 Y de los hijos de Imer, Hanani y Zebadías.
Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
21 Y de los hijos de Harim, Maasías, Elías, Semaías, Jehiel y Uzías.
Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
22 Y de los hijos de Pasur, Elioenai, Maasías, Ismael, Netanael, Jozabad y Elasa.
Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
23 Y de los levitas, Jozabad, Simei, Kelaia que es Kelita, Petaias, Juda y Eliezer.
Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
24 Y de los compositores de música, Eliasib; y de los encargados de las puertas, Salum y Telem y Uri.
Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
25 Y de Israel, los hijos de Paros: Ramías, Jezias, Malquías, Mijamín, Eleazar, Malquías, y Benaía.
Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
26 Y de los hijos de Elam, Matanías, Zacarías, Jehiel y Abdi, y Jeremot y Elías.
Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
27 Y de los hijos de Zatu, Elioenai, Eliasib, Matanias, y Jeremot y Zabad y Aziza.
Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
28 Y de los hijos de Bebai, Johanán, Hananías, Zabai, Atlai.
Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
29 Y de los hijos de Bani, Mesulam, Maluc y Adaía, Jasub, Seal, Ramot.
Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
30 Y de los hijos de Pahat-moab, Adna y Quelal, Benaia, Maasias, Matanias, Bezaleel y Binuy y Manasés.
Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
31 Y de los hijos de Harim, Eliezer, Isaías, Malquias, Semaías, Simeón,
Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
32 Benjamín, Maluc, Semarias.
Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
33 De los hijos de Hasum, Matenai, Matata, Zabad, Elifelet, Jeremai, Manasés, Simei.
Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
34 De los hijos de Bani, Maadai, Amram y Uel,
Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
35 Benaia, Bedias, Queluhi,
Benaiah, Bediah, Keluhi
36 Vanias, Meremot, Eliasib,
Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
37 Matanias, Matenai y Jaasai,
Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
38 Y Bani y Binuy, Simei;
Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
39 Y Selemias y Natán y Adaía,
Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
40 Macnadebai, Sasai, Sarai,
Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
41 Azareel y Selemias, Semarias,
Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
42 Salum, Amarias, Jose.
Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
43 De los hijos de Nebo: Jeiel, Matatias, Zabad, Zebina, Jadau y Joel, Benaia.
Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
44 Todos estos habían tomado esposas extranjeras; y algunas de ellas tenían esposas por las cuales tuvieron descendencia.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.

< Esdras 10 >